< Psalms 9 >
1 Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
Az éneklőmesternek a múthlabbén szerint; Dávid zsoltára. Dicsérlek Uram teljes szívemmel, hirdetem minden csudatételedet.
2 Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
Örülök és örvendezek tebenned, zengedezem, oh Magasságos, a te nevedet;
3 Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
Hogy az én ellenségeim meghátráltak, elbuktak és elvesztek a te orczád előtt;
4 Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
Hogy véghezvitted ítéletemet és ügyemet: az ítélő-székben ültél, mint igaz bíró.
5 Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
Megdorgáltad a pogányokat, elvesztetted a gonoszt: nevöket mindörökre kitörölted.
6 Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
Az ellenség megszünt, elpusztult örökre; és a városoknak, a miket feldúltál még az emlékezetök is elveszett.
7 Olúwa jẹ ọba títí láé; ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
Az Úr pedig örökké trónol, ítéletre készítette el az ő székét.
8 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo; yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
És ő megítéli a világot igazsággal, törvényt tesz a népeknek méltányosan.
9 Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
És lesz az Úr nyomorultak kővára, kővár a szükség idején.
10 Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ, nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
Azért te benned bíznak, a kik ismerik a te nevedet; mert nem hagytad el, Uram, a kik keresnek téged.
11 Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni; kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
Zengjetek az Úrnak, a ki Sionban lakik; hirdessétek a népek között az ő cselekedeteit.
12 Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí; òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
Mert számon kéri a kiontott vért, megemlékezik rólok, nem feledkezik el a szegények kiáltásáról.
13 Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi! Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
Könyörülj rajtam, Uram! lásd meg az én nyomorúságomat, a mely gyűlölőim miatt van, a ki felemelsz engem a halál kapuiból;
14 kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
Hogy hirdessem minden dicséretedet Sion leányának kapuiban; hadd örvendjek a te szabadításodban.
15 Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́; ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
Besülyedtek a pogányok a verembe, a melyet ástak; a hálóban, a melyet elrejtettek, megakadt a lábok.
16 A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀; àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
Megismertetett az Úr, ítéletet hozott; a gonoszt annak kezemunkájával ejtette el. (Higgajon, Szela)
17 Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run. (Sheol )
Seolba jutnak a gonoszok, oda minden nép, a mely elfeledkezik Istenről. (Sheol )
18 Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé, ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
Mert a szegény nem lesz végképen elfelejtve, a nyomorultak reménye sem vész el örökre.
19 Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí; jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
Kelj fel Uram, ne hatalmasodjék el a halandó; ítéltessenek meg a pogányok te előtted!
20 Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa; jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. (Sela)
Rettentsd meg, Uram, őket; tudják meg a pogányok, hogy halandók ők! (Szela)