< Psalms 9 >
1 Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
Thaburi ya Daudi Wee Jehova, nĩngũkũgooca na ngoro yakwa yothe; nĩngũgana maũndũ maku mothe ma magegania marĩa wĩkĩte.
2 Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
Nĩngũcanjamũka na ngene nĩ ũndũ waku. Nĩngũina rwĩmbo ngooce rĩĩtwa rĩaku, Wee Ũrĩ-Igũrũ-Mũno.
3 Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
Thũ ciakwa icookaga na thuutha, ikahĩngwo igathira irĩ mbere yaku.
4 Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
Nĩgũkorwo nĩũtiirĩrĩire kĩhooto gĩakwa na ciira wakwa; nĩũikarĩire gĩtĩ gĩaku kĩa ũnene, na ũgatua ciira na ũthingu.
5 Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
Nĩũrũithĩtie ndũrĩrĩ na ũkaniina andũ arĩa aaganu; namo marĩĩtwa mao ũkamatharia tene na tene.
6 Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
Thũ nĩũcikinyĩirie mwanangĩko ũtathiraga, nĩwanangĩte matũũra macio manene; o na kũririkanwo kwao nĩgũthirĩte.
7 Olúwa jẹ ọba títí láé; ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
Jehova athamakaga nginya tene; nĩahaandĩte gĩtĩ gĩake kĩa ũnene nĩguo atuanĩre ciira.
8 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo; yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
Nĩagatuĩra andũ a thĩ ciira na kĩhooto; nĩagathamakĩra ndũrĩrĩ o ta ũrĩa kwagĩrĩire.
9 Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
Jehova nĩwe rĩũrĩro rĩa arĩa ahinyĩrĩrie, kĩĩhitho kĩrĩ hinya hĩndĩ ya mathĩĩna.
10 Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ, nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
Arĩa mooĩ rĩĩtwa rĩaku nĩmarĩkwĩhokaga, nĩgũkorwo Jehova ndũrĩ watiganĩria arĩa makũrongoragia.
11 Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni; kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
Inĩrai Jehova nyĩmbo mũmũgooce, o ũcio ũikarĩire gĩtĩ gĩake kĩa ũnene kũu Zayuni; umbũrĩrai andũ a ndũrĩrĩ maũndũ marĩa ekĩte.
12 Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí; òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
Nĩgũkorwo ũcio ũrĩhanagĩria thakame nĩamaririkanaga; kĩrĩro kĩa andũ arĩa ahinyĩrĩrĩku ndakariganĩrwo nĩkĩo.
13 Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi! Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
Wee Jehova, ta rora wone ũrĩa thũ ciakwa iranyariira! Njiguĩra tha, ũnjoe na igũrũ, ũndute kuuma ihingo-inĩ cia gĩkuũ,
14 kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
nĩguo nyumbũre ũgooci waku ndĩ kũu ihingo-inĩ cia Mwarĩ wa Zayuni, na ndĩ kũu ngenagĩre ũhonokio waku.
15 Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́; ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
Ndũrĩrĩ nĩigwĩte o irima rĩrĩa cienjete; magũrũ maacio nĩmanyiitĩtwo nĩ wabu o ũcio ihithĩte wa gũtegana.
16 A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀; àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
Jehova nĩemenyithanĩtie na ũndũ wa gũtuanĩra ciira na kĩhooto gĩake; andũ arĩa aaganu nĩmetegete na wĩra wa moko mao ene.
17 Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run. (Sheol )
Andũ arĩa aaganu macookaga o mbĩrĩra-inĩ, ĩĩ-ni, ndũrĩrĩ iria ciothe iriganagĩrwo nĩ Ngai. (Sheol )
18 Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé, ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
No rĩrĩ, andũ arĩa abatari matigũtũũra mariganĩire, na kana mwĩhoko wa arĩa ahinyĩrĩrie ũthire nginya tene.
19 Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí; jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
Wee Jehova, arahũka, Ndũkareke mũndũ agĩe na ũhootani; reke ndũrĩrĩ ituĩrwo ciira irĩ mbere yaku.
20 Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa; jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. (Sela)
Wee Jehova, maiguithie guoya, ũreke ndũrĩrĩ imenye atĩ cio no andũ.