< Psalms 9 >

1 Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
Au maître chantre. Avec voix de jeunes filles. Sur bénites. Cantique de David. Je loue l'Éternel de tout mon cœur; je vais dire toutes tes merveilles,
2 Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
l'allégresse et la joie que je trouve en toi, chanter ton nom, ô Très-haut!
3 Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
Car mes ennemis se retirent en arrière, chancellent et disparaissent à ta vue!
4 Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
Car tu défends ma cause et mon droit, tu sièges sur ton trône en juste juge.
5 Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
Tu tances les peuples, détruis les impies, effaces leur nom pour toujours, à jamais.
6 Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
Mes ennemis sont perdus, ruines éternelles! Tu as détruit leurs villes, leur mémoire a péri!
7 Olúwa jẹ ọba títí láé; ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
Oui, l'Éternel règne à perpétuité, Il a pour le jugement disposé son trône,
8 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo; yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
et Il juge le monde avec justice, et rend aux peuples des sentences équitables.
9 Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
Et l'Éternel est un refuge pour le pauvre, un refuge dans les temps de détresse.
10 Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ, nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
Ils se confient en toi ceux qui connaissent ton nom; car tu ne délaisses pas ceux qui te cherchent, Éternel.
11 Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni; kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
Chantez l'Éternel, qui réside en Sion, racontez aux nations ses hauts faits!
12 Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí; òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
Car, vengeur du sang, Il se souvient d'eux, Il n'oublie pas le cri des malheureux.
13 Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi! Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
Sois-moi propice, Éternel! Vois la misère où mes ennemis me réduisent; retire-moi des portes de la mort,
14 kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
afin que je publie toute ta louange aux Portes de la fille de Sion, me réjouissant de ton secours!
15 Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́; ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
Les nations enfoncent dans la fosse qu'elles ont creusée; leur pied se prend au filet qu'elles ont caché.
16 A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀; àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
L'Éternel s'est montré; Il a fait justice, en enlaçant l'impie dans l'ouvrage même de ses mains. (Harpes. (Pause)
17 Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run. (Sheol h7585)
Les impies vont dans les Enfers, et de même tous les peuples qui ont oublié Dieu. (Sheol h7585)
18 Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé, ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
Car toujours le pauvre ne sera pas oublié, et l'espoir des malheureux n'est pas à jamais perdu.
19 Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí; jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
Lève-toi, Éternel, afin que l'homme ne s'élève pas, afin que les nations soient jugées devant toi!
20 Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa; jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. (Sela)
Mets, Éternel, ta terreur sur elles! que les peuples sentent qu'ils ne sont que des hommes. (Pause)

< Psalms 9 >