< Psalms 89 >

1 Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
Una contemplación de Ethan, el Ezrahita. Cantaré eternamente la bondad de Yahvé. Con mi boca, daré a conocer tu fidelidad a todas las generaciones.
2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
En efecto, declaro: “El amor se mantiene firme para siempre. Tú estableciste los cielos. Tu fidelidad está en ellos”.
3 Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
“He hecho un pacto con mi elegido, He jurado a David, mi siervo,
4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
‘Estableceré tu descendencia para siempre, y edificar tu trono por todas las generaciones”. (Selah)
5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
Los cielos alabarán tus maravillas, Yahvé, tu fidelidad también en la asamblea de los santos.
6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
Porque ¿quién en los cielos puede compararse con Yahvé? ¿Quién de los hijos de los seres celestiales es como Yahvé?
7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
un Dios muy asombroso en el consejo de los santos, para ser temido por encima de todos los que le rodean?
8 Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
Yahvé, Dios de los Ejércitos, ¿quién es un poderoso como tú? Yah, tu fidelidad te rodea.
9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
Tú gobiernas el orgullo del mar. Cuando sus olas se levantan, tú las calmas.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
Has hecho pedazos a Rahab, como a un muerto. Has dispersado a tus enemigos con tu poderoso brazo.
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
Los cielos son tuyos. La tierra también es tuya, el mundo y su plenitud. Tú los has fundado.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
Tú has creado el norte y el sur. El Tabor y el Hermón se alegran en tu nombre.
13 Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Tienes un brazo poderoso. Tu mano es fuerte, y tu diestra es exaltada.
14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
La rectitud y la justicia son el fundamento de tu trono. La bondad amorosa y la verdad van delante de tu rostro.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
Dichosos los que aprenden a aclamarte. Caminan a la luz de tu presencia, Yahvé.
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
En tu nombre se alegran todo el día. En tu justicia, son exaltados.
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
Porque tú eres la gloria de su fuerza. En su favor, nuestro cuerno será exaltado.
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Porque nuestro escudo pertenece a Yahvé, nuestro rey al Santo de Israel.
19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
Entonces hablaste en visión a tus santos, y dijo: “He dado fuerza al guerrero. He exaltado a un joven del pueblo.
20 Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
He encontrado a David, mi siervo. Lo he ungido con mi aceite santo,
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
con el que mi mano se establecerá. Mi brazo también lo fortalecerá.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Ningún enemigo le cobrará impuestos. Ningún malvado lo oprimirá.
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
Derrotaré a sus adversarios delante de él, y golpear a los que le odian.
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
Pero mi fidelidad y mi bondad estarán con él. En mi nombre, su cuerno será exaltado.
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
También pondré su mano sobre el mar, y su mano derecha en los ríos.
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
Me llamará: “Tú eres mi Padre”, mi Dios, y la roca de mi salvación”.
27 Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
También lo nombraré mi primogénito, el más alto de los reyes de la tierra.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
Guardaré mi bondad amorosa para él por siempre. Mi pacto se mantendrá firme con él.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
También haré que su descendencia sea eterna, y su trono como los días del cielo.
30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
Si sus hijos abandonan mi ley, y no camines en mis ordenanzas;
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
si rompen mis estatutos, y no guardan mis mandamientos;
32 nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
entonces castigaré su pecado con la vara, y su iniquidad con azotes.
33 ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
Pero no le quitaré del todo mi bondad amorosa, ni permitir que falle mi fidelidad.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
No romperé mi pacto, ni alterar lo que mis labios han pronunciado.
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
Una vez he jurado por mi santidad, No voy a mentir a David.
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
Su descendencia será eterna, su trono como el sol ante mí.
37 A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
Se establecerá para siempre como la luna, el testigo fiel en el cielo”. (Selah)
38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
Pero tú has rechazado y despreciado. Te has enfadado con tu ungido.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
Has renunciado al pacto de tu siervo. Has ensuciado su corona en el polvo.
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
Has derribado todos sus setos. Has llevado sus fortalezas a la ruina.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
Todos los que pasan por el camino le roban. Se ha convertido en un reproche para sus vecinos.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
Has exaltado la mano derecha de sus adversarios. Has hecho que todos sus enemigos se alegren.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
Sí, tú haces retroceder el filo de su espada, y no lo han apoyado en la batalla.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
Has acabado con su esplendor, y arrojó su trono al suelo.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
Has acortado los días de su juventud. Lo has cubierto de vergüenza. (Selah)
46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
¿Hasta cuándo, Yahvé? ¿Te vas a esconder para siempre? ¿Arderá su ira como el fuego?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
Recuerda lo corto que es mi tiempo, ¡para qué vanidad has creado a todos los hijos de los hombres!
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol h7585)
¿Qué hombre es el que vivirá y no verá la muerte? ¿quién librará su alma del poder del Seol? (Selah) (Sheol h7585)
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
Señor, ¿dónde están tus antiguas bondades? que juraste a David en tu fidelidad?
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
Acuérdate, Señor, del reproche de tus siervos, cómo llevo en mi corazón las burlas de todos los pueblos poderosos,
51 ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
Con que tus enemigos se han burlado, Yahvé, con la que se han burlado de los pasos de tu ungido.
52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
Benditosea Yahvé por siempre. Amén, y amén.

< Psalms 89 >