< Psalms 89 >

1 Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
Maschil al lui Etan ezrahitul. Voi cânta îndurările DOMNULUI pentru totdeauna, din generație în generație voi face cunoscută credincioșia ta cu gura mea.
2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
Căci am spus: Mila va fi zidită pentru totdeauna, credincioșia ta o vei întemeia chiar în ceruri.
3 Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
Am făcut legământ cu alesul meu, i-am jurat lui David, servitorul meu,
4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
Sămânța ta o voi întemeia pentru totdeauna și îți voi zidi tronul din generație în generație. (Selah)
5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
Și cerurile vor lăuda minunile tale, DOAMNE, credincioșia ta de asemenea în adunarea sfinților.
6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
Pentru că cine din cer poate fi comparat cu DOMNUL? Cine dintre fiii celor tari poate fi asemănat cu DOMNUL?
7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
Dumnezeu este foarte de temut în adunarea sfinților și respectat de toți cei din jurul lui.
8 Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
DOAMNE Dumnezeul oștirilor, cine este DOMN puternic asemenea ție? Sau cine este asemenea credincioșiei tale dimprejurul tău?
9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
Tu stăpânești furia mării, când valurile ei se ridică, tu le liniștești.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
Ai rupt Rahabul în bucăți, ca pe unul care este ucis; ai împrăștiat pe dușmanii tăi cu brațul tău puternic.
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
Cerurile sunt ale tale, pământul de asemenea este al tău, cât despre lume și plinătatea ei, tu le-ai fondat.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
Nordul și sudul, tu le-ai creat, Taborul și Hermonul se vor bucura în numele tău.
13 Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Tu ai un braț tare, puternică este mâna ta și înaltă este dreapta ta.
14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
Dreptatea și judecata sunt locuința tronului tău, mila și adevărul vor merge înaintea feței tale.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
Binecuvântat este poporul care cunoaște sunetul bucuriei, ei vor umbla, DOAMNE, în lumina înfățișării tale.
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
În numele tău se vor bucura toată ziua și în dreptatea ta vor fi înălțați.
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
Căci tu ești gloria puterii lor și în favoarea ta cornul nostru va fi înălțat.
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Pentru că DOMNUL este apărarea noastră; și Sfântul lui Israel este al nostru împărat.
19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
Atunci ai vorbit în viziune sfântului tău și ai spus: Am fost ajutor unuia tare; am înălțat pe unul ales din popor.
20 Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
Am găsit pe David, servitorul meu; cu untdelemnul meu sfânt l-am uns,
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
El, cu care mâna mea va fi întemeiată, brațul meu de asemenea îl va întări.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Dușmanul nu va stoarce de la el, nici fiul stricăciunii nu îl va chinui.
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
Și voi înfrânge pe dușmanii lui înaintea feței sale și voi lovi cu plăgi pe cei ce îl urăsc.
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
Dar credincioșia mea și mila mea vor fi cu el și în numele meu va fi cornul lui înălțat.
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
Voi pune mâna lui de asemenea în mare și mâna lui dreaptă în râuri.
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
El va striga către mine: Tu ești tatăl meu, Dumnezeul meu și stânca salvării mele.
27 Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
Eu, de asemenea, îl voi face întâiul meu născut și mai înalt decât împărații pământului.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
Mila mea o voi păstra pentru el pentru totdeauna, și legământul meu va fi neclintit cu el.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
Sămânța lui de asemenea o voi face să continue întotdeauna și tronul lui precum zilele cerurilor.
30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
Dacă copiii lui părăsesc legea mea și nu umblă în judecățile mele,
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
Dacă strică statutele mele și nu țin poruncile mele,
32 nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
Atunci voi pedepsi fărădelegea lor cu nuiaua și nelegiuirea lor cu lovituri.
33 ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
Cu toate acestea bunătatea mea iubitoare nu mi-o voi retrage cu totul de la el, nici nu voi permite să eșueze credincioșia mea.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
Nu voi rupe legământul meu, nici nu voi schimba ce a ieșit de pe buzele mele.
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
O dată am jurat prin sfințenia mea că nu voi minți pe David.
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
Sămânța lui va dăinui pentru totdeauna și tronul lui, ca soarele, înaintea mea.
37 A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
Ca luna va fi întemeiat pentru totdeauna și ca un martor credincios în ceruri. (Selah)
38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
Dar tu ai lepădat și ai detestat, te-ai înfuriat pe unsul tău.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
Ai anulat legământul servitorului tău, i-ai întinat coroana, aruncând-o la pământ.
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
Ai dărâmat toate gardurile lui; ai adus întăriturile lui la ruină.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
Toți cei ce trec pe lângă cale îl pradă, el este o ocară pentru vecinii lui.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
Ai înălțat dreapta potrivnicilor lui; ai făcut pe toți dușmanii lui să se bucure.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
Tu, de asemenea, ai întors tăișul sabiei lui și nu l-ai susținut în bătălie.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
Ai făcut să înceteze gloria lui și ai aruncat tronul lui la pământ.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
Ai scurtat zilele tinereții sale, l-ai acoperit cu rușine. (Selah)
46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
Până când, DOAMNE? Te vei ascunde pentru totdeauna? Va arde furia ta ca un foc?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
Amintește-ți ce scurt este timpul meu. Oare în zadar ai făcut pe toți fiii oamenilor?
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol h7585)
Ce om trăiește și nu va vedea moartea? Își va elibera el sufletul din mâna mormântului? (Selah) (Sheol h7585)
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
Doamne, unde sunt bunătățile tale iubitoare de mai înainte, pe care le-ai jurat lui David în adevărul tău?
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
Amintește-ți, Doamne, ocara servitorilor tăi; că port în sânul meu ocara tuturor oamenilor tari;
51 ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
Ocara cu care dușmanii tăi au ocărât, DOAMNE; cu care au ocărât pașii unsului tău.
52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
Binecuvântat fie DOMNUL pentru totdeauna. Amin și Amin.

< Psalms 89 >