< Psalms 89 >

1 Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
Pieśń pouczający Etana Ezrachity. Będę śpiewać o miłosierdziu PANA na wieki, swymi ustami będę głosił twoją wierność przez wszystkie pokolenia.
2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
Powiedziałem bowiem: Miłosierdzie będzie budowane na wieki, na niebiosach utwierdziłeś swoją wierność.
3 Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
Zawarłem przymierze z moim wybrańcem; przysiągłem Dawidowi, swemu słudze;
4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
Na wieki utwierdzę twoje potomstwo i zbuduję twój tron na wszystkie pokolenia. (Sela)
5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
PANIE, niebiosa wysławiają twoje cuda i twoją wierność w zgromadzeniu świętych.
6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
Któż bowiem na niebie może się równać z PANEM? [Kto] pośród synów mocarzy jest podobny do PANA?
7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
Bóg jest straszliwy w zgromadzeniu świętych i budzi grozę wśród wszystkich, [którzy są] wokół niego.
8 Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
PANIE, Boże zastępów, któż [jest] jak ty, PAN mocny? Twoja wierność bowiem cię otacza.
9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
Ty panujesz nad wzburzonym morzem; gdy się podnoszą jego fale, ty je poskramiasz.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
Ty zmiażdżyłeś Rahaba jak rannego, mocą twego ramienia rozproszyłeś swoich wrogów.
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
Twoje [są] niebiosa, twoja też ziemia; ty ugruntowałeś świat i wszystko, co go napełnia.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
Ty stworzyłeś północ i południe; Tabor i Hermon śpiewają o twoim imieniu.
13 Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Twoje ramię jest mocne, twoja ręka potężna, a twoja prawica wzniesiona.
14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
Sprawiedliwość i sąd są podstawą twego tronu, miłosierdzie i prawda idą przed twoim obliczem.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
Błogosławiony lud, który zna okrzyk radości; będzie chodzić w świetle twego oblicza, PANIE.
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
W twoim imieniu będą się weselić każdego dnia, a w twojej sprawiedliwości będą wywyższeni.
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
Ty bowiem jesteś chwałą ich mocy i z twojej woli nasz róg będzie wzniesiony.
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Bo PAN jest naszą tarczą, a Święty Izraela naszym królem.
19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
Powiedziałeś wtedy w widzeniu do twego świętego: Udzieliłem pomocy mocarzowi, wywyższyłem wybranego z ludu.
20 Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
Znalazłem Dawida, mego sługę, namaściłem go swoim świętym olejem.
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
Moja ręka będzie przy nim i wzmocni go moje ramię.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Nie będzie uciskany przez wroga, a syn nieprawości go nie pognębi.
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
Zetrę na jego oczach jego przeciwników, a tych, którzy go nienawidzą, powalę.
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
Ponadto moja prawda i miłosierdzie będą z nim, a w moim imieniu jego róg będzie wzniesiony.
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
I położę na morzu jego rękę i na rzekach jego prawicę.
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
On zawoła: Ty jesteś moim ojcem, moim Bogiem i skałą mego zbawienia.
27 Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
Ja też uczynię go pierworodnym [i] najwyższym wśród królów ziemi.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
Na wieki zachowam dla niego swoje miłosierdzie, a moje przymierze z nim będzie trwałe.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
Jego potomstwo utrwalę na wieki, a jego tron – jak dni niebios.
30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
Ale jeśli jego synowie porzucą moje prawo i nie będą postępowali według moich nakazów;
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
Jeśli moje ustawy znieważą, a moich przykazań nie będą przestrzegać;
32 nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
Wtedy ukarzę rózgą ich przestępstwo, a ich nieprawość biczami.
33 ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
Ale nie odbiorę mu mojego miłosierdzia ani nie zawiodę w mojej wierności.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
Nie złamię mego przymierza ani nie zmienię tego, co wyszło z moich ust.
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
Raz przysiągłem na moją świętość, że nie skłamię Dawidowi.
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
Jego potomstwo będzie trwać na wieki, a jego tron jak słońce przede mną;
37 A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
Jak księżyc będzie utwierdzone na wieki i [jak] wierny świadek na niebie. (Sela)
38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
A jednak odrzuciłeś [go] i wzgardziłeś nim, rozgniewałeś się na twego pomazańca.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
Zerwałeś przymierze z twoim sługą, strąciłeś na ziemię jego koronę.
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
Zburzyłeś wszystkie jego płoty i rozwaliłeś jego baszty.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
Grabią go wszyscy, którzy przechodzą drogą; stał się pośmiewiskiem dla swoich sąsiadów.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
Podniosłeś prawicę jego przeciwników, sprawiłeś radość wszystkim jego wrogom.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
Stępiłeś też ostrze jego miecza i nie wsparłeś go w walce.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
Położyłeś koniec jego chwale, a jego tron obaliłeś na ziemię.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
Skróciłeś dni jego młodości, okryłeś go hańbą. (Sela)
46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
Jak długo, PANIE? Czy wiecznie będziesz się ukrywał? Czy twoja zapalczywość będzie płonąć jak ogień?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
Pamiętaj, jak krótkie jest moje życie; czy na próżno stworzyłeś wszystkich synów ludzkich?
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol h7585)
Któż z ludzi może żyć i nie ujrzeć śmierci? [Któż] wyrwie swą duszę z mocy grobu? (Sela) (Sheol h7585)
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
Gdzie są, o Panie, twoje dawne łaski, [które] przysiągłeś Dawidowi w swej prawdzie?
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
Pamiętaj, Panie, o zniewadze twoich sług; [o tym], że noszę w swym zanadrzu [wzgardę] wszystkich możnych narodów;
51 ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
Którą twoi wrogowie znieważają, PANIE, którą znieważają ścieżki twego pomazańca.
52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
Błogosławiony [niech będzie] PAN na wieki. Amen, amen.

< Psalms 89 >