< Psalms 89 >
1 Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
Maskîl d’Ethân l’Esrahite. Toujours je chanterai les bontés du Seigneur; d’âge en âge, ma bouche proclamera ta fidélité.
2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
Car, dis-je, la bonté aura une durée éternelle; dans les cieux tu as rendu immuable ta fidélité.
3 Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
"J’Ai conclu une alliance avec mon élu, fait un serment à mon serviteur David.
4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
Jusque dans l’éternité j’affermirai tes descendants, et maintiendrai ton trône de génération en génération." (Sélah)
5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
Et les cieux célèbrent tes merveilles, ô Seigneur, l’assemblée des saints ta fidélité.
6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
Car qui, au-dessus des, nuages, rivalise avec l’Eternel, égale le Seigneur parmi les fils des dieux?
7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
Dieu est infiniment révéré dans la réunion des saints, redoutable à tout ce qui l’entoure.
8 Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
Seigneur, Dieu-Cebaot, qui comme toi, est éternellement puissant? Ta fidélité rayonne autour de toi.
9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
Tu domines l’orgueil de la mer; quand ses vagues se soulèvent, tu apaises leur fureur.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
Tu as écrasé la fière Egypte comme un blessé à mort; par ton bras puissant tu as dispersé tes ennemis.
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
A toi le ciel! à toi aussi la terre! L’Univers et ce qu’il renferme, c’est toi qui as tout fondé.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
Le nord et le midi, c’est toi qui les as créés; le Thabor et le Hermon acclament ton nom.
13 Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Ton bras est armé de force, puissante est ta main, sublime ta droite.
14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
La justice et le droit sont la base de ton trône, l’amour et la vérité marchent devant toi.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
Heureux le peuple connaissant les chants de victoire, cheminant, Eternel, à la lumière de ta face!
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
Sans cesse ils sont en joie à cause de ton nom, et s’élèvent par ta justice.
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
Car la parure de leur force, c’est toi; par ta bienveillance s’élève notre puissance.
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Oui, notre défenseur s’appuie sur l’Eternel, notre roi sur le Saint d’Israël.
19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
Jadis tu parlas, dans une vision, à ton pieux serviteur, tu disais: "J’Ai donné mon appui à un héros, j’ai grandi un élu sorti du peuple.
20 Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
J’Ai trouvé David, mon serviteur; avec mon huile sainte, je l’ai consacré,
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
lui, à qui ma main servira de soutien, et que mon bras armera de force.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
Aucun ennemi ne saura le circonvenir, ni aucun malfaiteur l’humilier.
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
J’Écraserai devant lui ses agresseurs, et ceux qui le haïssent, je les abattrai.
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
Ma fidélité et ma bonté seront avec lui, et par mon nom grandira sa puissance.
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
J’Établirai sa domination sur la mer, et son empire sur les fleuves.
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
Il me dira: "Tu es mon père, mon Dieu et le rocher de mon salut!"
27 Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
En retour, je ferai de lui mon premier-né, supérieur aux rois de la terre.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
Éternellement je lui conserverai mon amour, et mon alliance avec lui demeurera solide.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
Je ferai durer toujours sa postérité, et son trône aussi longtemps que les cieux.
30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
Que si ses enfants abandonnent ma loi et refusent de suivre mes statuts,
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
s’ils violent mes préceptes et désobéissent à mes commandements,
32 nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
je châtierai leur rébellion avec une verge, leur impiété par des fléaux.
33 ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
Mais je ne lui retirerai pas mon amour, je ne mentirai pas à ma promesse.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
Je ne trahirai pas mon alliance, et l’énoncé de mes lèvres, je ne le changerai pas.
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
Une fois que j’ai juré par ma sainteté que je ne tromperai pas la confiance de David,
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
sa postérité durera éternellement, et son trône sera stable devant moi à l’égal du soleil;
37 A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
comme la lune, il sera à jamais inébranlable: dans les cieux vit un témoin fidèle." (Sélah)
38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
Et pourtant tu l’as délaissé, rejeté, ton élu; tu t’es emporté contre lui.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
Tu as rompu l’alliance de ton serviteur, dégradé, jeté à terre son diadème.
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
Tu as démoli toutes ses murailles, changé en ruines ses châteaux forts.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
Tous les passants l’ont mis au pillage, il est devenu un objet d’opprobre pour ses voisins.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
Tu as élevé la droite de ses adversaires, rempli de joie tous ses ennemis.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
Tu fais reculer le tranchant de son épée, tu ne le soutiens pas dans les combats.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
Tu as mis fin à sa splendeur, et son trône, tu l’as fait crouler à terre.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
Tu as abrégé les jours de sa jeunesse, et tu l’as enveloppé de honte. (Sélah)
46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
Jusqu’à quand, ô Eternel, te déroberas-tu obstinément, et ta colère brûlera-t-elle comme du feu?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
Rappelle-toi combien je suis éphémère, combien est vaine la vie que tu donnes à tous les fils d’Adam.
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol )
Est-il un homme qui demeure en vie, sans voir venir la mort? Qui pourra soustraire son âme aux prises du Cheol? (Sélah) (Sheol )
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
Où sont tes anciens bienfaits, Seigneur, que, dans ta sincérité, tu avais promis à David?
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
Souviens-toi, Seigneur, des outrages dirigés contre tes serviteurs, que j’ai eu à porter dans mon sein, de la part de peuples si nombreux;
51 ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
outrages dont tes ennemis, Eternel, m’abreuvent, qu’ils déversent sur les pas de ton oint!
52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
Loué soit l’Eternel à jamais! Amen et Amen!