< Psalms 89 >

1 Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
Yahweh, I will sing forever about the ways you faithfully love me; people not yet born will hear that you faithfully [do all that you have promised].
2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
I will tell people that you will faithfully love us forever, and that your being faithful [to do what you have promised] is as permanent as the sky.
3 Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
Yahweh said, “I have made an agreement with David, whom I chose [to serve me]. I have made this solemn (agreement with/promise to) him:
4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
‘I will enable various ones of your descendants to always be kings; the line of kings descended from you [MTY] will never end.’”
5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
Yahweh, I desire that all [those beings who are in] [MTY] heaven will praise you for the wonderful things that you do, and that all your holy angels will sing about how you faithfully [do what you promise].
6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
There is no one [RHQ] in heaven who can be compared with you, Yahweh. There are no angels [RHQ] in heaven who are equal to you.
7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
When your holy angels gather together, they declare that you must be revered; they say that you are more awesome than all the angels that surround your throne!
8 Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
O Yahweh, God Almighty, there is no one [RHQ] who is powerful like you are; your faithfully doing [all that you promise] is [like a cloak that] [MET] [always] surrounds you.
9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
You rule over the powerful seas; when their waves rise up, you calm them.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
You are the one who crushed [and killed the great sea monster named] Rahab. You [defeated and] scattered your enemies with your great power [MTY].
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
The heavens are yours, and the earth is yours; and everything on the earth is yours, because you created it all.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
You created [everything from] the north to the south. Tabor [Mountain] and Hermon [Mountain] joyfully praise you [MTY].
13 Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
(You/Your arms) are very powerful; (you/your hands) are extremely strong.
14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
(Your rule [MTY] over us is based on/As you rule over us, you are always) treating people fairly and justly, and on/are always faithfully loving us and doing [what you promised].
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
Yahweh, happy are the people who worship you with joyful shouts, who live knowing that you are always watching over them.
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
Every day, throughout the day, they rejoice in what you [MTY] [have done], and they praise you for being very good [to them].
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
You give us your glorious strength; because you act in our favor, we defeat [MET] [our enemies].
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Yahweh, you gave us [the one who] protects us [MET]; you, the holy God whom we Israelis worship, chose a king for us.
19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
Long ago you spoke in a vision to one of your servants/prophets, saying, “I have helped a famous soldier; I chose him from among all the people to be a king.
20 Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
That man is David, the one who will serve me [faithfully], and I anointed him with sacred olive oil [to make him king].
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
I [MTY] will always strengthen him; with my power [MTY] I will make him strong.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
His enemies will never find ways to defeat him, and wicked people will never defeat him.
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
I will crush his enemies in front of him and get rid of those who hate him.
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
I will always be loyal to him and faithfully love him and enable him to defeat [MET] [his enemies].
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
I will cause (his kingdom/the area that he rules) to include all the land from the [Mediterranean] Sea to the [Euphrates] River.
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
He will say to me, ‘You are my Father, my God, the one who protects [MET] and saves me.’
27 Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
I will give him [the rights/privileges that a man’s] firstborn son has [MET]; he will be the greatest king on the earth.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
I will always be loyal to him, and my agreement [to bless] him will last forever.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
I will establish a line of his descendants that will never end, various ones of his descendants will always be kings.
30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
But, if [some of] his descendants disobey my laws, and do not not behave like my commands say that they should,
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
if they disregard my requirements and do not do the right things that I have told them to do,
32 nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
I will punish them severely [MTY] and cause them to suffer for doing wrong.
33 ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
But I will not stop faithfully loving [David], and I will always do what I promised him.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
I will not break the agreement that I made with him; I will not change even one word that I spoke [to him].
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
Once I made a solemn promise to David, and that will never change, and because I am God, I will never lie to David.
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
[I promised that] the line of kings descended from him will go on forever; it will last as long as the sun [shines].
37 A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
That line will (be as permanent/last as long) as the moon that is always watching everything from the sky.
38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
But [Yahweh], now you have rejected [DOU] David! You are very angry with the king whom you appointed.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
[It seems that] you have broken the agreement that you made with your servant, [David]; it seems as though you [have signaled that he is no longer the king by] throwing his crown into the dust/dirt.
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
You have torn down the walls [that protect] his [city], and allowed all his forts to become ruins.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
All those who pass by plunder/steal his possessions; his neighbors (laugh at/ridicule) him.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
You have enabled his enemies to defeat him; you have made them all happy.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
You have caused his sword to become useless, and you have not helped him in his battles.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
You have caused his splendor to end (OR, You have taken away his power by knocking his throne to the ground.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
You have caused him to look old when he is still young and caused him to be very shamed/disgraced.
46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
O Yahweh, how long [will this continue]? Will you hide yourself forever? How long will your anger burn like a fire?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
Do not forget that life is very short; have you created all us people in vain?
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol h7585)
No one can [RHQ] keep on living and never die; (No one can [RHQ] avoid going/Everyone will go) to the place of the dead. (Sheol h7585)
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
Yahweh, you promised long ago that you would faithfully love us; why are you not doing that? You solemnly promised that to David!
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
Yahweh, do not forget that people insult me! (Heathen people/People who do not know you) curse me!
51 ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
Yahweh, your enemies insult your chosen king! They insult/ridicule him wherever he goes.
52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
I hope/desire that Yahweh will be praised forever! Amen! May it be so!

< Psalms 89 >