< Psalms 89 >
1 Maskili ti Etani ará Esra. Èmi kọrin títóbi ìfẹ́ Olúwa títí láé; pẹ̀lú ẹnu mi ní èmi yóò jẹ́ kí a mọ òtítọ́ rẹ láti ìran dé ìran.
The understanding of Ethan the Ezrahite. I will sing the mercies of the Lord in eternity. I will announce your truth with my mouth, from generation to generation.
2 Èmi ó wí pé, ìfẹ́ rẹ dúró títí láé, pé ìwọ gbe òtítọ́ rẹ kalẹ̀ ní ọ̀run fúnra rẹ̀.
For you have said: Mercy will be built in the heavens, unto eternity. Your truth will be prepared there.
3 Ìwọ wí pé, “Èmi ti dá májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn àyànfẹ́ mi mo ti búra fún Dafidi ìránṣẹ́ mi.
I have set up a covenant with my elect. I have sworn to David my servant:
4 ‘Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ múlẹ̀ títí láé èmí ó sì máa gbe ìtẹ́ rẹ ró láti ìran dé ìran.’”
I will prepare your offspring, even in eternity. And I will build up your throne, from generation to generation.
5 Àwọn ọ̀run yóò máa yin iṣẹ́ ìyanu rẹ, Olúwa, òtítọ́ rẹ ni ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.
The heavens will confess your miracles, Lord, and also your truth, in the Church of the saints.
6 Ta ni ó wà ní ọ̀run tí a lè fiwé Olúwa? Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fiwé Olúwa?
For who among the clouds is equal to the Lord? Who among the sons of God is like God?
7 Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọ́n bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi; ó sì ní ìbùyìn fún ju gbogbo àwọn tí ó yí i ká.
God is glorified by the counsel of the saints. He is great and terrible above all those who are around him.
8 Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí rẹ ìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ rẹ sì yí ọ ká.
O Lord, God of hosts, who is like you? You are powerful, Lord, and your truth is all around you.
9 Ìwọ ń darí ríru omi Òkun; nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn parọ́rọ́.
You rule over the power of the sea, and you even mitigate the movement of its waves.
10 Ìwọ ni ó ti ya Rahabu pẹ́rẹpẹ̀rẹ bí ẹni tí a pa; ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára rẹ tú àwọn ọ̀tá rẹ ká.
You have humbled the arrogant one, like one who has been wounded. You have scattered your enemies with the arm of your strength.
11 Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ́ tìrẹ: ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀: ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.
Yours are the heavens, and yours is the earth. You founded the whole world in all its fullness.
12 Gúúsù àti àríwá ìwọ ni ó dá wọn; Tabori àti Hermoni ń fi ayọ̀ yin orúkọ rẹ.
You created the north and the sea. Tabor and Hermon will exult in your name.
13 Ìwọ ní apá agbára; agbára ní ọwọ́ rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Your arm acts with power. Let your hand be strengthened, and let your right hand be exalted.
14 Òdodo àti òtítọ́ ni ìpìlẹ̀ ìtẹ́ rẹ: ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ síwájú rẹ.
Justice and judgment are the preparation of your throne. Mercy and truth will precede your face.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ ohùn ayọ̀ nì, Olúwa wọ́n ó máa rìn ní ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ.
Blessed is the people that knows jubilation. They will walk in the light of your countenance, O Lord,
16 Wọn ń ṣògo nínú orúkọ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́, wọn ń yin òdodo rẹ.
and they will exult in your name all day long, and they will be exalted in your justice.
17 Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn; nípa ojúrere ni ìwo wá ń ṣògo.
For you are the glory of their virtue, and in your goodness, our horn will be exalted.
18 Nítorí ti Olúwa ni asà wa, ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
For our assumption is of the Lord, and it is of our king, the holy one of Israel.
19 Nígbà náà ni ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran, sí àwọn olóòtítọ́ rẹ, wí pé, “Èmi ti gbé adé kalẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára, èmi ti gbé ẹni tí a yàn láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.
Then you spoke in a vision to your holy ones, and you said: I have stationed help with the powerful one, and I have exalted the elect one from my people.
20 Èmi ti rí Dafidi ìránṣẹ́ mi; pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ni mo fi yàn án.
I have found my servant David. I have anointed him with my holy oil.
21 Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú rẹ̀ apá mí yóò sì fi agbára fún un.
For my hand will assist him, and my arm will fortify him.
22 Àwọn ọ̀tá kì yóò borí rẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
The enemy will have no advantage over him, nor will the son of iniquity be positioned to harm him.
23 Èmi yóò run àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ èmi yóò lu àwọn tí ó kórìíra rẹ bolẹ̀.
And I will cut down his enemies before his face. And those who hate him, I will turn to flight.
24 Òtítọ́ mi àti ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú rẹ àti ní orúkọ mi ni a ó gbé ìwo rẹ ga.
And my truth and my mercy will be with him. And his horn will be exalted in my name.
25 Èmi ó gbé ọwọ́ rẹ lórí òkun, àti ọwọ́ ọ̀tún rẹ lórí àwọn odo ńlá.
And I will place his hand on the sea and his right hand on the rivers.
26 Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘Ìwọ ni baba mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
He will invoke me: “You are my father, my God, and the support of my salvation.”
27 Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mi, ẹni gíga ju àwọn ọba ayé.
And I will make him the first-born, preeminent before the kings of the earth.
28 Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un, àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
I will preserve my mercy for him eternally, and my covenant for him faithfully.
29 Èmi ó fi ìdí irú-ọmọ rẹ̀ múlẹ̀ títí láé, àti ìtẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
And I will set his offspring from generation to generation, and his throne like the days of heaven.
30 “Bí àwọn ọmọ rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀ tí wọn kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
But if his sons abandon my law, and if they do not walk in my judgments,
31 Tí wọn bá ba ìlànà mi jẹ́ tí wọn kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
if they profane my justices, and if they do not keep my commandments:
32 nígbà náà ni èmi ó fì ọ̀gọ̀ bẹ ìrékọjá wọn wò; àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú pàṣán;
I will visit their iniquities with a rod, and their sins with a beating.
33 ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò jẹ́ kí òtítọ́ mi kí ó yẹ̀.
But I will not scatter my mercy from him, and I will not do harm to my truth.
34 Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọ̀rọ̀ tí ó ti ẹnu mi jáde padà.
And I will not profane my covenant, and I will not make void that which proceeds from my lips.
35 Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ni èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra; èmi kì yóò purọ́ fún Dafidi.
I have sworn by my holiness one time: I will not lie to David,
36 Irú-ọmọ rẹ yóò dúró títí láé, àti ìtẹ́ rẹ̀ yóò dúró bí oòrùn níwájú mi.
his offspring will remain for eternity. And his throne will be like the sun in my sight,
37 A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá, àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run.” (Sela)
and, like the moon, it is perfected in eternity, and it is a faithful witness in heaven.
38 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí ìwọ ti ṣá tì, ìwọ sì kórìíra; ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró rẹ.
Yet, truly, you have rejected and despised, you have pushed away, my Christ.
39 Ìwọ ti sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ rẹ di òfo; ìwọ tàbùkù adé rẹ nínú eruku.
You have overthrown the covenant of your servant. You have profaned his sanctuary on earth.
40 Ìwọ ti wó gbogbo àwọn odi rẹ̀ ìwọ sọ ibi gíga rẹ̀ di ahoro.
You have destroyed all his fences. You have made his territory dreadful.
41 Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ; ó ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé rẹ̀.
All who pass by the way have plundered him. He has become a disgrace to his neighbors.
42 Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá rẹ̀ sókè; ìwọ mú gbogbo ọ̀tá rẹ̀ yọ̀.
You have exalted the right hand of those who oppress him. You have brought joy to all his enemies.
43 Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà rẹ̀ padà, ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.
You have diverted the help of his sword, and you have not assisted him in battle.
44 Ìwọ ti mú ògo rẹ̀ kùnà, ìwọ si wó ìtẹ́ rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.
You have torn him away from cleansing, and you have smashed his throne down to the ground.
45 Ìwọ ti gé ọjọ́ èwe rẹ̀ kúrú; ìwọ sì fi ìtìjú bò ó.
You have reduced the days of his time. You have flooded him with confusion.
46 Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa? Tí ìwọ ó ha fi ara rẹ pamọ́ títí láé? Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú rẹ yóò máa jó bí iná?
How long, O Lord? Will you turn away unto the end? Will your wrath flare up like a fire?
47 Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tó nítorí asán ha ni ìwọ fi ṣẹ̀dá àwọn ènìyàn!
Remember what my substance is. For could you really have appointed all the sons of men in vain?
48 Ta ni yóò wà láààyè tí kò ní rí ikú rẹ̀? Ta ló lè sá kúrò nínú agbára isà òkú? (Sheol )
Who is the man that will live, and yet not see death? Who will rescue his own soul from the hand of the underworld? (Sheol )
49 Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ rẹ àtijọ́ wà, tí ìwọ ti fi òtítọ́ rẹ búra fún Dafidi?
O Lord, where are your mercies of antiquity, just as you swore to David in your truth?
50 Rántí, Olúwa, bí a ti ń gan àwọn ìránṣẹ́ rẹ; bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,
Be mindful, O Lord, of the disgrace of your servants (which I have sustained in my sinews) among many nations.
51 ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá rẹ gàn, Olúwa, tí wọn gan ipasẹ̀ ẹni àmì òróró rẹ.
With these, your enemies have reproached you, O Lord; with these, they have reproached the commutation of your Christ.
52 Olùbùkún ní Olúwa títí láé.
Blessed is the Lord for all eternity. Amen. Amen.