< Psalms 87 >
1 Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin. Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
Psaume des enfants de Coré. — Cantique. Les fondements de Jérusalem reposent Sur les montagnes saintes.
2 Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
L'Éternel aime les portes de Sion; Il la préfère à toutes les demeures de Jacob.
3 Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀, ìlú Ọlọ́run,
Un avenir de gloire t'est destiné, cité de Dieu! (Pause)
4 “Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi: Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi, yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’”
Je mentionnerai l'Egypte et Babylone Parmi ceux qui me connaissent. Ainsi que les Philistins, et Tyr, et l'Ethiopie: C'est ici que sera leur lieu de naissance!
5 Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ, “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀, àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
Oui, on dira de Sion: «Chacun d'eux est né dans cette ville, Et le Très-Haut lui-même l'a fondée!»
6 Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀: “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
L'Éternel passe en revue les peuples, et il écrit: «Celui-là aussi est un enfant de Sion!» (Pause)
7 Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu ohun èlò orin yóò wí pé, “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”
Alors chanteurs et joueurs de flûte disent de concert: En toi se trouvent toutes mes sources de vie!»