< Psalms 87 >

1 Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin. Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
Un psaume par les fils de Korah; un chant. Son fondement est dans les montagnes saintes.
2 Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
Yahvé aime les portes de Sion plus que toutes les habitations de Jacob.
3 Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀, ìlú Ọlọ́run,
On dit de toi des choses glorieuses, cité de Dieu. (Selah)
4 “Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi: Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi, yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’”
J'inscrirai Rahab et Babylone parmi ceux qui me reconnaissent. Voici la Philistie, Tyr, et aussi l'Éthiopie: « Celui-ci est né là-bas. »
5 Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ, “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀, àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
Oui, on dira de Sion: « Untel et untel sont nés en elle ». le Très-Haut lui-même l'établira.
6 Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀: “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
L'Éternel fera le compte, quand il écrira les peuples, « Celui-ci est né là. (Selah)
7 Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu ohun èlò orin yóò wí pé, “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”
Ceux qui chantent comme ceux qui dansent disent, « Tous mes ressorts sont en toi. »

< Psalms 87 >