< Psalms 87 >

1 Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin. Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
“By the sons of Korach; a psalm or song.” It is founded by him on holy mountains.
2 Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
The Lord loveth the gates of Zion more than all the dwellings of Jacob.
3 Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀, ìlú Ọlọ́run,
Glorious things are spoken of thee, O city of God. (Selah)
4 “Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi: Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi, yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’”
I will make mention of Rahab and Babylon as those that know me; behold, here is Philistia, and Tyre, with Ethiopia: “This man was born there.”
5 Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ, “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀, àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
But of Zion will it be said, “This and that man were born in her:” and the Most High himself doth establish her.
6 Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀: “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
The Lord will number when he writeth down nations. “This man was born there.” (Selah)
7 Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu ohun èlò orin yóò wí pé, “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”
And the singers as well as the players on instruments shall be there: all my springs [of joy] are in thee.

< Psalms 87 >