< Psalms 87 >

1 Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin. Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
A Psalme or song committed to the sonnes of Korah. God layde his foundations among the holy mountaines.
2 Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
The Lord loueth the gates of Zion aboue all the habitations of Iaakob.
3 Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀, ìlú Ọlọ́run,
Glorious things are spoken of thee, O citie of God. (Selah)
4 “Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi: Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi, yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’”
I will make mention of Rahab and Babel among them that knowe me: beholde Palestina and Tyrus with Ethiopia, There is he borne.
5 Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ, “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀, àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
And of Zion it shall be sayde, Many are borne in her: and he, euen the most High shall stablish her.
6 Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀: “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
The Lord shall count, when hee writeth the people, He was borne there. (Selah)
7 Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu ohun èlò orin yóò wí pé, “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”
Aswell the singers as the players on instruments shall prayse thee: all my springs are in thee.

< Psalms 87 >