< Psalms 86 >
1 Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
Молитва Давидова.
2 Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Бережи мою душу, бо я богобі́йний, спаси Ти, мій Боже, Свого раба, що на Тебе наді́ю кладе́!
3 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
Змилосе́рдься до мене, о Господи, бо я кличу до Тебе ввесь день,
4 Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
потіш душу Свого раба, бо до Тебе підно́шу я, Господи, душу мою,
5 Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
бо Ти, Господи, добрий і вибачли́вий, і многомилости́вий для всіх, хто кли́че до Тебе!
6 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
Почуй же, о Господи, молитву мою, і вислухай голос блага́ння мого, —
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
в день недолі своєї я кличу до Тебе, бо Ти обізве́шся до мене!
8 Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
Нема, Господи, поміж бога́ми такого, як Ти, і чинів нема, як чи́ни Твої!
9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
Всі наро́ди, яких Ти створи́в, поприхо́дять і попадають перед лице́м Твоїм, Господи, та Ім'я́ Твоє сла́вити будуть,
10 Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
великий бо Ти, та чу́да вчиняєш, Ти — Бог єдиний!
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
Дорогу Свою покажи мені, Господи, і я бу́ду ходити у правді Твоїй, приєдна́й моє серце боятися Йме́ння Твого́!
12 Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
Я буду всім серцем своїм вихваля́ти Тебе, Господи, Боже Ти мій, і сла́вити буду повіки Ім'я́ Твоє,
13 Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol )
велика бо милість Твоя надо мною, і вирвав Ти душу мою від шео́лу глибокого! (Sheol )
14 Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
Боже, злочинці повстали на мене, а на́товп гноби́телів прагне моєї душі, і перед собою не ставлять Тебе.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
А Ти, Господи, Бог щедрий і милосердний, довготерпели́вий і многомилости́вий, і справедли́вий, —
16 Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
зглянься на мене, й помилуй мене, подай же Своєму рабові Свою силу, і спаси сина Своєї неві́льниці!
17 Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.
Учини мені знака на добре, — і нехай це побачать мої ненави́сники, і хай засоро́млені будуть, бо Ти, Господи, мені допоміг та мене звесели́в!