< Psalms 86 >

1 Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
He inoi na Rawiri. Whakatitahatia iho tou taringa, e Ihowa whakahokia mai he kupu ki ahau; he ware hoki ahau, he rawakore.
2 Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Tiakina toku wairua: he tapu hoki ahau; mau, e toku Atua, e whakaora tau pononga e whakawhirinaki atu nei ki a koe.
3 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
Tohungia ahau, e te Ariki: e karanga nei hoki ahau ki a koe i te ra roa nei.
4 Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
Whakaharitia te wairua o tau pononga; ka ara atu nei hoki toku wairua, e te Ariki, ki a koe.
5 Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
He pai hoki koe, e te Ariki, he ngawari: e ranea ana hoki tau mahi tohu ki te hunga katoa e karanga ana ki a koe.
6 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
Tahuri mai tou taringa, e Ihowa, ki taku inoi: whakarongo kitoku reo unene.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
Ka karanga ahau ki a koe i te ra o toku pouri: e whakahoki kupu mai hoki koe ki ahau.
8 Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
Kahore he rite mou, e te Ariki, i roto i nga atua: kahore hoki he rite mo au mahi.
9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
Ka haere mai nga iwi katoa i hanga e koe, a ka koropiko ki tou aroaro, e te Ariki; ka whakakororia hoki i tou ingoa.
10 Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
He nui hoki koe, e mahi ana i nga mea whakamiharo: ko koe anake te Atua.
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
Whakaakona ahau ki tau ara, e Ihowa; ka haere ahau i runga i tou pono: whakatapatahitia toku ngakau ki te wehi i tou ingoa.
12 Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
Ka whakamoemiti katoa toku ngakau ki a koe, e te Ariki, e toku Atua: ka whakakororia ano i tou ingoa ake ake.
13 Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol h7585)
He nui hoki tau mahi tohu ki ahau: a kua whakaorangia e koe toku wairua i te reinga i raro riro. (Sheol h7585)
14 Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
E te Atua, kua whakatika ki ahau te hunga whakakake: kua whaia ano toku wairua e te huihuinga o te hunga tutu; kahore hoki koe e waiho i to ratou aroaro.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
Ko koe ia, e te Ariki, he Atua atawhai, he tohu tangata: he puhoi ki te riri, e hua ana te mahi tohu me te pono.
16 Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
Tahuri mai ki ahau, tohungia hoki ahau: homai tou kaha ki tau pononga, whakaorangia te tama a tau pononga wahine.
17 Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.
Whakakitea mai ki ahau he tohu mo te pai: kia kite ai te hunga e kino ana ki ahau, kia whakama ai: nou e Ihowa i awhina i ahau, i whakamarie i ahau.

< Psalms 86 >