< Psalms 86 >

1 Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
Prière de David. Prête l'oreille ô Éternel, exauce-moi; Car je suis affligé et misérable.
2 Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Protège mon âme; car je suis de ceux qui t'aiment. Mon Dieu, sauve ton serviteur qui se confie en toi!
3 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
Aie pitié de moi, Seigneur; Car je crie vers toi tout le jour.
4 Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
Réjouis l'âme de ton serviteur: C'est à toi. Seigneur, que j'élève mon âme!
5 Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
Car tu es bon et clément. Seigneur, Et riche en grâce pour tous ceux qui t'invoquent.
6 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
Écoute ma prière, ô Éternel, Et sois attentif à ma voix suppliante!
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
Je t'invoque au jour de ma détresse, Parce que tu m'exauces.
8 Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
Nul parmi les dieux n'est comme toi. Seigneur, Et il n'est point d'oeuvres comme les tiennes.
9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
Toutes les nations que tu as faites Viendront se prosterner devant toi. Seigneur, Et elles glorifieront ton nom.
10 Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
Car tu es grand, et tu accomplis des miracles: Toi seul, tu es Dieu!
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
Eternel, apprends-moi à marcher dans tes voies: Je suivrai le chemin de ta vérité. Dispose mon coeur à la crainte de ton nom.
12 Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
Je te louerai, Seigneur, mon Dieu, de tout mon coeur. Et je glorifierai ton nom à toujours;
13 Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol h7585)
Car ta bonté est grande envers moi, Et tu as retiré mon âme du fond du Sépulcre. (Sheol h7585)
14 Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
O Dieu, des orgueilleux se lèvent contre moi. Des bandes d'hommes violents en veulent à ma vie; Ils ne pensent jamais à toi.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
Mais toi, Seigneur, tu es un Dieu Compatissant et miséricordieux. Lent à la colère, riche en grâce et en fidélité.
16 Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
Tourne-toi vers moi et prends-moi en pitié. Donne ta force à ton serviteur. Et sauve le fils de ta servante.
17 Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.
Accorde-moi un signe de ta faveur, Afin que mes ennemis soient couverts de confusion, Et qu'ils voient que c'est toi, ô Éternel, Qui me secours et me consoles!

< Psalms 86 >