< Psalms 86 >
1 Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
Prière de David. Prête l'oreille ô Éternel, exauce-moi; Car je suis affligé et misérable.
2 Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Protège mon âme; car je suis de ceux qui t'aiment. Mon Dieu, sauve ton serviteur qui se confie en toi!
3 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
Aie pitié de moi, Seigneur; Car je crie vers toi tout le jour.
4 Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
Réjouis l'âme de ton serviteur: C'est à toi. Seigneur, que j'élève mon âme!
5 Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
Car tu es bon et clément. Seigneur, Et riche en grâce pour tous ceux qui t'invoquent.
6 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
Écoute ma prière, ô Éternel, Et sois attentif à ma voix suppliante!
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
Je t'invoque au jour de ma détresse, Parce que tu m'exauces.
8 Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
Nul parmi les dieux n'est comme toi. Seigneur, Et il n'est point d'oeuvres comme les tiennes.
9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
Toutes les nations que tu as faites Viendront se prosterner devant toi. Seigneur, Et elles glorifieront ton nom.
10 Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
Car tu es grand, et tu accomplis des miracles: Toi seul, tu es Dieu!
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
Eternel, apprends-moi à marcher dans tes voies: Je suivrai le chemin de ta vérité. Dispose mon coeur à la crainte de ton nom.
12 Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
Je te louerai, Seigneur, mon Dieu, de tout mon coeur. Et je glorifierai ton nom à toujours;
13 Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol )
Car ta bonté est grande envers moi, Et tu as retiré mon âme du fond du Sépulcre. (Sheol )
14 Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
O Dieu, des orgueilleux se lèvent contre moi. Des bandes d'hommes violents en veulent à ma vie; Ils ne pensent jamais à toi.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
Mais toi, Seigneur, tu es un Dieu Compatissant et miséricordieux. Lent à la colère, riche en grâce et en fidélité.
16 Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
Tourne-toi vers moi et prends-moi en pitié. Donne ta force à ton serviteur. Et sauve le fils de ta servante.
17 Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.
Accorde-moi un signe de ta faveur, Afin que mes ennemis soient couverts de confusion, Et qu'ils voient que c'est toi, ô Éternel, Qui me secours et me consoles!