< Psalms 86 >
1 Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
Prière de David. Prête l’oreille, Yahweh, exauce-moi, car je suis malheureux et indigent.
2 Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Garde mon âme, car je suis pieux; sauve ton serviteur, ô mon Dieu; il met sa confiance en toi.
3 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
Aie pitié de moi, Seigneur, car je crie vers toi tout le jour.
4 Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
Réjouis l’âme de ton serviteur, car vers toi, Seigneur, j’élève mon âme.
5 Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
Car tu es bon, Seigneur, et clément, et plein de compassion pour tous ceux qui t’invoquent.
6 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
Yahweh, prête l’oreille à ma prière, sois attentif à la voix de mes supplications.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
Je t’invoque au jour de ma détresse, et tu m’exauceras.
8 Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
Nul ne t’égale parmi les dieux, Seigneur, rien ne ressemble à tes œuvres.
9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
Toutes les nations que tu as faites viendront se prosterner devant toi, Seigneur, et rendre gloire à ton nom.
10 Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
Car tu es grand et tu opères des prodiges; toi seul, tu es Dieu.
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
Enseigne-moi tes voies Yahweh; je veux marcher dans ta fidélité; attache mon cœur à la crainte de ton nom.
12 Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
Je te louerai de tout mon cœur, Seigneur, mon Dieu; et je glorifierai ton nom à jamais.
13 Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol )
Car ta bonté est grande envers moi, tu as tiré mon âme du fond du schéol. (Sheol )
14 Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
Ô Dieu, des orgueilleux se sont élevés contre moi, une troupe d’hommes violents en veulent à ma vie, sans tenir aucun compte de toi.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
Mais toi, Seigneur, tu es un Dieu miséricordieux et compatissant, lent à la colère, riche en bonté et en fidélité.
16 Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
Tourne vers moi tes regards et aie pitié de moi; donne ta force à ton serviteur, et sauve le fils de ta servante.
17 Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.
Signale ta bonté envers moi: que mes ennemis le voient et soient confondus! Car c’est toi, Yahweh, qui m’assistes et me consoles.