< Psalms 86 >

1 Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
David Lawkthuihaih. Aw Angraeng, na naa to patueng ah loe, na pathim ah; kai loe kamtang hoi kavawt kami ah ni ka oh.
2 Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Ka ciim pongah, ka hinghaih hae pathlung ah; Nang loe ka Sithaw ah ni na oh; nang oephaih tawn na tamna hae pahlong ah!
3 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
Aw Angraeng, ka nuiah palungnathaih tawn raeh; ni thokkruek nang khaeah ka hangh.
4 Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
Na tamna ih pakhra to anghoesak ah; Aw Angraeng, nang khaeah, ka hinghaih kang vah tahang.
5 Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
Angraeng, nang loe na hoih, zae tahmen hanah na koeh; nang kawk kaminawk boih khaeah, pop parai palungnathaih to nam tuengsak.
6 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
Aw Angraeng, lawk ka thuihaih hae tahngai ah; tahmen kang hnikhaih lok hae tahngai raeh.
7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
Raihaih ka tongh niah nang to kang kawk han; to naah nang mah nang pathim tih.
8 Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
Aw Angraeng, sithawnawk thungah nang baktih mi doeh om ai; na sak ih toknawk baktih tok doeh om ai.
9 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
Aw Angraeng, na sak ih prae congca kaminawk angzo o tih; nihcae loe na hmaa ah tabok o ueloe, na hmin to pakoeh o tih.
10 Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
Nang loe lensawk moe, dawnrai hmuennawk to na sak; Sithaw ah kaom loe nang khue ni.
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
Aw Angraeng, loklam na patuek ah; kai loe na loktang lok pongah ni ka caeh han; na hmin ka zit thaih hanah, ka palungthin hae amhongsak ah.
12 Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
Aw ka Angraeng Sithaw, ka palungthin boih hoiah kang pakoeh han; dungzan khoek to na hmin kang pakoeh han.
13 Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol h7585)
Na palungnathaih loe kating ai len; kathuk taprong thung hoiah ka hinghaih to nang pahlong boeh. (Sheol h7585)
14 Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
Aw Sithaw, amoek kaminawk loe naeh hanah angthawk o tahang; tahmenhaih tawn ai amkhueng kaminawk loe nang to hmaloe koek ah suem o ai, nihcae loe ka hinghaih to pakrong o.
15 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
Toe Aw Angraeng, nang loe tahmenhaih, amlunghaih, pauep thaihaih, pop parai palungnathaih, loktang lok hoiah koi Sithaw ah na oh.
16 Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
Kai khaeah angqoi ah loe, ka nuiah palungnathaih to tawn ah; na tamna khaeah na thacakhaih to paek ah loe, na tamna nongpata ih capa hae pahlong ah.
17 Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.
Kai hnuma kaminawk mah a hnuk o thaih moe, azat o thaih hanah, kai han angmathaih kahoih to na patuek ah; tih pongah tih nahaeloe Angraeng nang mah nang bomh moe, nang pathloep boeh.

< Psalms 86 >