< Psalms 85 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa; ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
Смиловао си се, Господе, на земљу своју, повратио си робље Јаковљево.
2 Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. (Sela)
Опростио си неправду народу свом, покрио си све грехе његове.
3 Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
Зауставио си сву јарост своју, ублажио жестину гнева свог.
4 Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa, kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Поврати нас Боже, Спаситељу наш, прекини срдњу своју на нас.
5 Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé? Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
Зар ћеш се довека гневити на нас, и протегнути гнев свој од колена на колено?
6 Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́, pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
Зар се нећеш повратити и оживети нас, да би се народ Твој радовао о Теби?
7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa, kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
Покажи нам, Господе, милост своју, и помоћ своју дај нам.
8 Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí; ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
Да послушам шта говори Господ Бог. Он изриче мир народу свом и свецима својим, и онима који се обраћају срцем к Њему.
9 Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
Да, близу је оних који Га се боје помоћ Његова, да би населио славу у земљи нашој!
10 Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀; òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
Милост и истина срешће се, правда и мир пољубиће се.
11 Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
Истина ће никнути из земље и правда ће с неба проникнути.
12 Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́, ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
И Господ ће дати добро, и земља наша даће плод свој.
13 Òdodo síwájú rẹ lọ o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.
Правда ће пред Њим ићи, и поставиће на пут стопе своје.

< Psalms 85 >