< Psalms 85 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa; ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
Przedniejszemu śpiewakowi synom Korego psalm. Łaskęś, Panie! niekiedy pokazywał ziemi twojej; przywróciłeś zasię z niewoli Jakóba.
2 Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. (Sela)
Odpuściłeś nieprawość ludu twojego, pokryłeś wszelki grzech ich. (Sela)
3 Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
Uśmierzyłeś wszystek gniew twój, odwróciłeś od zapalczywości popędliwość twoję.
4 Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa, kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Przywróć nas, o Boże zbawienia naszego; a uczyń wstręt gniewowi swemu przeciwko nam.
5 Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé? Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
Izali na wieki gniewać się będziesz na nas? a rozciągniesz gniew twój od rodzaju do rodzaju?
6 Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́, pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
Izali ty obróciwszy się, nie ożywisz nas, tak, aby się lud twój rozradował w tobie?
7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa, kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
Panie! okaż nam miłosierdzie twoje, a daj nam zbawienie swoje.
8 Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí; ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
Ale posłucham, co rzecze Bóg, on Pan mocny; zaiste mówi pokój do ludu swego, i do świętych swoich, byle się jedno zaś do głupstwa nie wracali.
9 Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
Zaisteć bliskie jest zbawienie jego tym, którzy się go boją; a przebywać będzie chwała jego w ziemi naszej.
10 Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀; òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
Miłosierdzie i prawda spotkają się z sobą; sprawiedliwość i pokój pocałują się.
11 Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
Prawda z ziemi wyrośnie, a sprawiedliwość z nieba wyjrzy.
12 Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́, ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
Da też Pan i doczesne dobra, a ziemia nasza wyda owoc swój.
13 Òdodo síwájú rẹ lọ o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.
Sprawi, że sprawiedliwość przed twarzą jego pójdzie, gdy postawi na drodze nogi swoje.

< Psalms 85 >