< Psalms 85 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa; ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
U A lokomaikai mai oe, e Iehova, i kou aina; Ua hoihoi mai oe i ke pio ana o ka Iakoba.
2 Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. (Sela)
Ua kala mai oe i ka hewa o kou poe kanaka, Ua uhi mai oe i ko lakou hala a pau. (Sila)
3 Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
Ua lawe aku oe i kou inaina a pau, Ua huli aku no hoi oe, mai ka wela o kou huhu aku.
4 Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa, kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
E hoohuli mai oe ia makou, e ke Akua o ko makou ola, A e hooki hoi oe i kou huhu mai ia makou.
5 Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé? Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
E huhu mau loa mai anei oe ia makou? E hooloihi aku anei oe i kou huhu ia hanauna aku, ia hanauna aku?
6 Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́, pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
Aole anei oe e hoihoi mai i ko makou ola ana? I hauoli ai kou poe kanaka ia oe.
7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa, kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
E hoike mai oe, e Iehova, i kou lokomaikai ia makou, A e haawi mai hoi kou hoola ana na makou.
8 Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí; ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
E hoolohe aku no au i ka mea a ke Akua a Iehova e olelo mai ai; No ka mea, e hai mai no oia i ka malu no kona poe kanaka, a me kona poe haipule: Mai hoi hou nae lakou i ka mea lapuwale.
9 Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
Oiaio, ua kokoke mai no kona hoola ana i ka poe makau aku ia ia; I noho ka hanohano ma ko kakou aina.
10 Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀; òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
Ua halawai pu ke aloha me ka oiaio; Ua honi pu no hoi ka pono me ka maluhia.
11 Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
E ulu mai no ka oiaio mailoko mai o ka honua, A mai ka lani mai hoi e nana mai ai ka pono.
12 Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́, ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
E haawi mai no o Iehova i ka maikai; A e haawi mai no hoi ko kakou aina i kona hua iho.
13 Òdodo síwájú rẹ lọ o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.
E hele ae no ka pono imua o kona alo; A e alakai hoi oia ia kakou ma ke ala o kona mau kapuwai.

< Psalms 85 >