< Psalms 85 >
1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa; ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
Pour la fin, aux fils de Coré, psaume. Vous avez béni, Seigneur, votre terre; vous avez détourné la captivité de Jacob.
2 Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. (Sela)
Vous avez remis l’iniquité de votre peuple, vous avez couvert tous leurs péchés.
3 Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
Vous avez apaisé votre colère, vous avez détourné votre peuple de la colère de votre indignation.
4 Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa, kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Convertissez-nous, ô Dieu notre Sauveur; et détournez votre colère de nous.
5 Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé? Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
Est-ce que vous serez éternellement en colère; ou étendrez-vous votre colère de génération en génération?
6 Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́, pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
Ô Dieu, revenez à nous, vous nous donnerez la vie, et votre peuple se réjouira en vous.
7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa, kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
Montrez-nous, Seigneur, votre miséricorde; et donnez-nous votre salut.
8 Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí; ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
J’écouterai ce que dira au dedans de moi le Seigneur Dieu, parce qu’il parlera paix pour son peuple, Et pour ses saints, et pour ceux qui se tournent vers leur cœur.
9 Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
Assurément, près de ceux qui le craignent est son salut, afin que la gloire habite dans notre terre.
10 Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀; òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
La miséricorde et la vérité se sont rencontrées; la justice et la paix se sont donné un baiser.
11 Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
La vérité est sortie de la terre, et la justice a regardé du haut du ciel.
12 Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́, ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
Le Seigneur accordera sa bonté, et notre terre donnera son fruit.
13 Òdodo síwájú rẹ lọ o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.
La justice marchera devant lui, et il mettra ses pas dans la voie.