< Psalms 85 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa; ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
Yahweh, you have been kind to [us people who live in] this land; you have enabled [us] Israeli people to become prosperous again.
2 Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. (Sela)
You forgave [us], your people, for the sins that we had committed; you pardoned [us] for all our sins [DOU].
3 Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
You stopped being angry [with us] and turned away from severely punishing [us].
4 Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa, kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
Now, God, the one who saves/rescues us, (restore us/make us prosperous again) and stop being angry with us!
5 Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé? Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
(Will you continue to be angry with us forever?/Please do not continue to be angry with us forever.) [DOU, RHQ]
6 Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́, pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
Please enable us [RHQ] to prosper again in order that [we], your people, will rejoice about what you [have done for us].
7 Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa, kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
Yahweh, by rescuing us [from our troubles/difficulties], show us that you faithfully love us.
8 Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí; ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
I want to listen to what Yahweh [our] God says, because he promises/says that he will enable [us], his people, to live peacefully, if we do not return to doing foolish things.
9 Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
He is surely ready to save/rescue those who revere him, in order that [his] glory/splendor will be seen in our land.
10 Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀; òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
[When that happens], he will both faithfully love us and faithfully [do for us what he promised to do] [PRS]; and we will act/behave righteously, and he will give us peace, which will be like a kiss that he gives us.
11 Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
Here on earth, we will (be loyal to/continually believe in) God, and from heaven, God will act justly/fairly [toward us].
12 Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́, ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
Yes, Yahweh will do good things [for us], and there will be great harvests in our land.
13 Òdodo síwájú rẹ lọ o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.
[Yahweh always acts] righteously [PRS, MET]; he acts righteously wherever he goes.

< Psalms 85 >