< Psalms 84 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ibùgbé rẹ̀ ti lẹ́wà tó, Olúwa àwọn ọmọ-ogun!
Psaume des enfants de Coré, [donné] au maître chantre, [pour le chanter] sur Guittith. Eternel des armées, combien sont aimables tes Tabernacles!
2 Ọkàn mi ń ṣàfẹ́rí nítòótọ́ ó tilẹ̀ pòǹgbẹ fún àgbàlá Olúwa àyà mi àti ara mi ń kọrin ayọ̀ sí Ọlọ́run alààyè.
Mon âme désire ardemment, et même elle défaut après les parvis de l'Eternel; mon cœur et ma chair tressaillent de joie après le [Dieu] Fort et vivant.
3 Nítòótọ́ ológoṣẹ́ ri ilé, ẹyẹ alápáǹdẹ̀dẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ fún ara rẹ̀, níbi tí yóò máa pa ọmọ rẹ̀ mọ́ sí: ibùgbé ní tòsí pẹpẹ rẹ̀, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọba mí àti Ọlọ́run mi.
Le passereau même a bien trouvé sa maison, et l'hirondelle son nid, où elle a mis ses petits; tes autels, ô Eternel des armées! mon Roi, et mon Dieu!
4 Ìbùkún ní fún àwọn tí ó ń gbé inú ilé rẹ; wọn ó máa yìn ọ́ títí láé.
Ô que bien-heureux sont ceux qui habitent en ta maison, et qui te louent incessamment! (Sélah)
5 Ìbùkún ni fún àwọn tí agbára wọn wà nínú rẹ àwọn tí wọ́n gbé ọkàn lé bíbẹ ibi mímọ́ wò.
Ô que bien-heureux est l'homme dont la force est en toi, et ceux au cœur desquels sont les chemins battus!
6 Àwọn tí ń la àfonífojì omijé lọ wọn sọ ọ́ di kànga àkọ́rọ̀ òjò sì fi ìbùkún bò ó.
Passant par la vallée de Baca ils la réduisent en fontaine; la pluie aussi comble les marais.
7 Wọ́n ń lọ láti ipa dé ipá títí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan fi farahàn níwájú Ọlọ́run ní Sioni.
Ils marchent avec force pour se présenter devant Dieu en Sion.
8 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa Ọlọ́run Alágbára; tẹ́tí sí mi, Ọlọ́run Jakọbu.
Eternel Dieu des armées, écoute ma requête; Dieu de Jacob, prête l'oreille; (Sélah)
9 Wo asà wa, Ọlọ́run; fi ojú àánú wò àwọn ẹni àmì òróró rẹ.
Ô Dieu, notre bouclier, vois, et regarde la face de ton Oint.
10 Dídára ní ọjọ́ kan ní ààfin rẹ ju ẹgbẹ̀rún ọjọ́ lọ; èmi o kúkú máa ṣe aṣọ́nà nínú ilé Ọlọ́run mi jù láti gbé ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú.
Car mieux vaut un jour en tes parvis, que mille [ailleurs]. J'aimerais mieux me tenir à la porte en la maison de mon Dieu, que de demeurer dans les tentes des méchants.
11 Nítorí Olúwa Ọlọ́run jẹ́ òòrùn àti asà; Olúwa fún ni ní ojúrere àti ọlá; kò sí ohun rere kan tí yóò fàsẹ́yìn fún àwọn tí ó rìn ní àìlábùkù.
Car l'Eternel Dieu nous est un soleil et un bouclier; l'Eternel donne la grâce et la gloire, et il n'épargne aucun bien à ceux qui marchent dans l'intégrité.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Eternel des armées, ô que bien-heureux est l'homme qui se confie en toi!

< Psalms 84 >