< Psalms 84 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ibùgbé rẹ̀ ti lẹ́wà tó, Olúwa àwọn ọmọ-ogun!
Au chef des chantres. Sur la Ghitit. Par les fils de Koré. Psaume. Que tes demeures sont aimables, Eternel-Cebaot!
2 Ọkàn mi ń ṣàfẹ́rí nítòótọ́ ó tilẹ̀ pòǹgbẹ fún àgbàlá Olúwa àyà mi àti ara mi ń kọrin ayọ̀ sí Ọlọ́run alààyè.
Mon âme soupirait et languissait après les parvis du Seigneur: que mon cœur, tout mon être célèbrent le Dieu vivant!
3 Nítòótọ́ ológoṣẹ́ ri ilé, ẹyẹ alápáǹdẹ̀dẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ fún ara rẹ̀, níbi tí yóò máa pa ọmọ rẹ̀ mọ́ sí: ibùgbé ní tòsí pẹpẹ rẹ̀, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọba mí àti Ọlọ́run mi.
Même le passereau trouve un abri, l’hirondelle a son nid où elle dépose ses petits. Moi, je rêvais de tes autels, Eternel-Cebaot, mon roi et mon Dieu.
4 Ìbùkún ní fún àwọn tí ó ń gbé inú ilé rẹ; wọn ó máa yìn ọ́ títí láé.
Heureux ceux qui habitent dans ta maison, et sans cesse récitent tes louanges! (Sélah)
5 Ìbùkún ni fún àwọn tí agbára wọn wà nínú rẹ àwọn tí wọ́n gbé ọkàn lé bíbẹ ibi mímọ́ wò.
Heureux l’homme qui met sa force en toi, dont le cœur connaît les vraies routes!
6 Àwọn tí ń la àfonífojì omijé lọ wọn sọ ọ́ di kànga àkọ́rọ̀ òjò sì fi ìbùkún bò ó.
En traversant la vallée des larmes, ils en font un pays de sources, qu’en outre une pluie précoce couvre de bénédictions.
7 Wọ́n ń lọ láti ipa dé ipá títí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan fi farahàn níwájú Ọlọ́run ní Sioni.
Ils s’avancent avec une force toujours croissante, pour paraître devant Dieu à Sion.
8 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa Ọlọ́run Alágbára; tẹ́tí sí mi, Ọlọ́run Jakọbu.
Eternel, Dieu-Cebaot, écoute donc ma prière, prête l’oreille, Dieu de Jacob. (Sélah)
9 Wo asà wa, Ọlọ́run; fi ojú àánú wò àwọn ẹni àmì òróró rẹ.
Regarde, ô Dieu, celui qui est notre bouclier, fixe les yeux sur la face de ton oint.
10 Dídára ní ọjọ́ kan ní ààfin rẹ ju ẹgbẹ̀rún ọjọ́ lọ; èmi o kúkú máa ṣe aṣọ́nà nínú ilé Ọlọ́run mi jù láti gbé ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú.
Assurément, un jour dans tes parvis vaut mieux que mille autres; je préfère me tenir au seuil de la maison de mon Dieu, plutôt que de séjourner dans les tentes de l’impiété.
11 Nítorí Olúwa Ọlọ́run jẹ́ òòrùn àti asà; Olúwa fún ni ní ojúrere àti ọlá; kò sí ohun rere kan tí yóò fàsẹ́yìn fún àwọn tí ó rìn ní àìlábùkù.
Car le Seigneur Dieu est un soleil, un bouclier: l’Eternel octroie grâce et honneurs; il ne refuse pas le bonheur à ceux qui marchent dans la droiture.
12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Eternel-Cebaot, heureux l’homme qui a confiance en toi!

< Psalms 84 >