< Psalms 83 >
1 Orin. Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, má ṣe dákẹ́; má ṣe dákẹ́, Ọlọ́run má ṣe dúró jẹ́ẹ́.
A Song, — A Psalm of Asaph. O God, let there be no silence to Thee, Be not silent, nor be quiet, O God.
2 Wo bí àwọn ọ̀tá rẹ ti ń rọ́kẹ̀kẹ̀ lọ, bi àwọn ọ̀tá rẹ ti ń gbé ohùn wọn sókè.
For, lo, Thine enemies do roar, And those hating Thee have lifted up the head,
3 Pẹ̀lú àrékérekè ni wọn dìtẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ; wọn sí dìtẹ̀ mọ́ àwọn tí o fẹ́.
Against Thy people they take crafty counsel, And consult against Thy hidden ones.
4 Wọn wí pé, “wá, ẹ jẹ́ kí á pa wọ́n run bí orílẹ̀-èdè, kí orúkọ Israẹli ma bá a sí ní ìrántí mọ́.”
They have said, 'Come, And we cut them off from [being] a nation, And the name of Israel is not remembered any more.'
5 Wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú ọkàn kan; wọ́n ṣe àdéhùn láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ
For they consulted in heart together, Against Thee a covenant they make,
6 Àgọ́ Edomu àti ti àwọn ará Iṣmaeli, ti Moabu àti ti Hagari
Tents of Edom, and Ishmaelites, Moab, and the Hagarenes,
7 Gebali, Ammoni àti Amaleki, Filistia, pẹ̀lú àwọn ènìyàn Tire.
Gebal, and Ammon, and Amalek, Philistia with inhabitants of Tyre,
8 Asiria pẹ̀lú ti darapọ̀ mọ́ wọn láti ran àwọn ọmọ Lọti lọ́wọ́. (Sela)
Asshur also is joined with them, They have been an arm to sons of Lot. (Selah)
9 Ṣe sí wọn bí ìwọ ti ṣe sí Midiani bí o ti ṣe sí Sisera àti Jabini ní odò Kiṣoni,
Do to them as [to] Midian, As [to] Sisera, as [to] Jabin, at the stream Kishon.
10 ẹni tí ó ṣègbé ní Endori tí wọn sì dàbí ààtàn ní orí ilẹ̀.
They were destroyed at Endor, They were dung for the ground!
11 Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí Orebu àti Seebu, àwọn ọmọ-aládé wọn bí Seba àti Salmunna,
Make their nobles as Oreb and as Zeeb, And as Zebah and Zalmunna all their princes,
12 tí ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a gbà ní ìní àní pápá oko tútù Ọlọ́run.”
Who have said, 'Let us occupy for ourselves The comely places of God.'
13 Ìwọ Ọlọ́run, ṣe wọ́n bí ààjà, bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́.
O my God, make them as a rolling thing, As stubble before wind.
14 Bí iná ti í jó igbó, àti bí ọ̀wọ́-iná ti ń mú òkè ńlá gbiná,
As a fire doth burn a forest, And as a flame setteth hills on fire,
15 bẹ́ẹ̀ ni kí o fi ẹ̀fúùfù líle rẹ lépa wọn dẹ́rùbà wọn lójú pẹ̀lú ìjì rẹ.
So dost Thou pursue them with Thy whirlwind, And with Thy hurricane troublest them.
16 Fi ìtìjú kún ojú wọn, kí àwọn ènìyàn bá à lè ṣe àfẹ́rí orúkọ rẹ àti kí o fi ìjì líle rẹ dẹ́rùbà, ìwọ Olúwa.
Fill their faces [with] shame, And they seek Thy name, O Jehovah.
17 Jẹ́ kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọ́n sì dààmú láéláé kí wọ́n ṣègbé sínú ẹ̀gàn
They are ashamed and troubled for ever, Yea, they are confounded and lost.
18 jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ìwọ, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa: pé ìwọ nìkan ní Ọ̀gá-ògo jùlọ lórí gbogbo ayé.
And they know that Thou — (Thy name [is] Jehovah — by Thyself, ) [Art] the Most High over all the earth!