< Psalms 83 >

1 Orin. Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, má ṣe dákẹ́; má ṣe dákẹ́, Ọlọ́run má ṣe dúró jẹ́ẹ́.
“A psalm of Asaph.” O God! keep not silence! Hold not thy peace, and be not still, O God!
2 Wo bí àwọn ọ̀tá rẹ ti ń rọ́kẹ̀kẹ̀ lọ, bi àwọn ọ̀tá rẹ ti ń gbé ohùn wọn sókè.
For, lo! thine enemies roar, And they who hate thee lift up their heads.
3 Pẹ̀lú àrékérekè ni wọn dìtẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ; wọn sí dìtẹ̀ mọ́ àwọn tí o fẹ́.
For they form secret plots against thy people, And consult together against thy chosen ones.
4 Wọn wí pé, “wá, ẹ jẹ́ kí á pa wọ́n run bí orílẹ̀-èdè, kí orúkọ Israẹli ma bá a sí ní ìrántí mọ́.”
“Come,” say they, “let us blot them out from the number of the nations, That the name of Israel may no more be remembered!”
5 Wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú ọkàn kan; wọ́n ṣe àdéhùn láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ
With one consent they consult together, Against thee do they form a league, —
6 Àgọ́ Edomu àti ti àwọn ará Iṣmaeli, ti Moabu àti ti Hagari
The tents of Edom and the Ishmaelites, Of Moab and the Hagarenes,
7 Gebali, Ammoni àti Amaleki, Filistia, pẹ̀lú àwọn ènìyàn Tire.
Gebal and Ammon and Amalek, The Philistines, with the inhabitants of Tyre.
8 Asiria pẹ̀lú ti darapọ̀ mọ́ wọn láti ran àwọn ọmọ Lọti lọ́wọ́. (Sela)
The Assyrians also are joined with them; They lend their strength to the children of Lot.
9 Ṣe sí wọn bí ìwọ ti ṣe sí Midiani bí o ti ṣe sí Sisera àti Jabini ní odò Kiṣoni,
Do to them as to the Midianites, As to Sisera, as to Jabin at the brook Kison,
10 ẹni tí ó ṣègbé ní Endori tí wọn sì dàbí ààtàn ní orí ilẹ̀.
Who perished at Endor, And were trampled like dung to the earth.
11 Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí Orebu àti Seebu, àwọn ọmọ-aládé wọn bí Seba àti Salmunna,
Make their chiefs like Oreb and Zeeb; Yea, all their princes as Zeba and Zalmunna!
12 tí ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a gbà ní ìní àní pápá oko tútù Ọlọ́run.”
Who say, “Let us seize on God's habitations!”
13 Ìwọ Ọlọ́run, ṣe wọ́n bí ààjà, bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́.
Make them, O my God! like whirling chaff; Like stubble before the wind!
14 Bí iná ti í jó igbó, àti bí ọ̀wọ́-iná ti ń mú òkè ńlá gbiná,
As fire consumeth the forest, And as flame setteth the mountains in a blaze,
15 bẹ́ẹ̀ ni kí o fi ẹ̀fúùfù líle rẹ lépa wọn dẹ́rùbà wọn lójú pẹ̀lú ìjì rẹ.
So pursue them with thy tempest, And terrify them with thy storm!
16 Fi ìtìjú kún ojú wọn, kí àwọn ènìyàn bá à lè ṣe àfẹ́rí orúkọ rẹ àti kí o fi ìjì líle rẹ dẹ́rùbà, ìwọ Olúwa.
Cover their faces with shame, That they may seek thy name, O LORD!
17 Jẹ́ kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọ́n sì dààmú láéláé kí wọ́n ṣègbé sínú ẹ̀gàn
Let them be confounded! Yea, let them be put to shame, and perish!
18 jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ìwọ, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa: pé ìwọ nìkan ní Ọ̀gá-ògo jùlọ lórí gbogbo ayé.
That they may know that thy name alone is Jehovah; That thou art the Most High over all the earth.

< Psalms 83 >