< Psalms 83 >
1 Orin. Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, má ṣe dákẹ́; má ṣe dákẹ́, Ọlọ́run má ṣe dúró jẹ́ẹ́.
Píseň a žalm Azafův. Bože, neodmlčujž se, nečiň se neslyše, aniž se upokojuj, ó Bože silný.
2 Wo bí àwọn ọ̀tá rẹ ti ń rọ́kẹ̀kẹ̀ lọ, bi àwọn ọ̀tá rẹ ti ń gbé ohùn wọn sókè.
Nebo aj, nepřátelé tvoji se bouří, a ti, kteříž tě v nenávisti mají, pozdvihují hlavy.
3 Pẹ̀lú àrékérekè ni wọn dìtẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ; wọn sí dìtẹ̀ mọ́ àwọn tí o fẹ́.
Chytře tajné rady proti lidu tvému skládají, a radí se proti těm, kteréž ty skrýváš,
4 Wọn wí pé, “wá, ẹ jẹ́ kí á pa wọ́n run bí orílẹ̀-èdè, kí orúkọ Israẹli ma bá a sí ní ìrántí mọ́.”
Říkajíce: Poďte, a vyhlaďme je, ať nejsou národem, tak aby ani zpomínáno nebylo více jména Izraelova.
5 Wọ́n gbìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú ọkàn kan; wọ́n ṣe àdéhùn láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ
Jednomyslněť se na tom spolu snesli, i smlouvou se proti tobě zavázali,
6 Àgọ́ Edomu àti ti àwọn ará Iṣmaeli, ti Moabu àti ti Hagari
Stánkové Idumejští a Izmaelitští, Moábští a Agarenští,
7 Gebali, Ammoni àti Amaleki, Filistia, pẹ̀lú àwọn ènìyàn Tire.
Gebálští a Ammonitští, a Amalechitští, Filistinští s obyvateli Tyrskými.
8 Asiria pẹ̀lú ti darapọ̀ mọ́ wọn láti ran àwọn ọmọ Lọti lọ́wọ́. (Sela)
Ano i Assyrští spojili se s nimi, jsouce na ruku synům Lotovým. (Sélah)
9 Ṣe sí wọn bí ìwọ ti ṣe sí Midiani bí o ti ṣe sí Sisera àti Jabini ní odò Kiṣoni,
Učiniž jim jako Madianským, jako Zizarovi, a jako Jabínovi při potoku Císon,
10 ẹni tí ó ṣègbé ní Endori tí wọn sì dàbí ààtàn ní orí ilẹ̀.
Kteříž jsou do konce vyhlazeni v Endor, a učiněni hnůj země.
11 Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí Orebu àti Seebu, àwọn ọmọ-aládé wọn bí Seba àti Salmunna,
Nalož s nimi a s vůdci jejich jako s Gorébem, jako s Zébem, jako s Zebahem, a jako s Salmunou, se všemi knížaty jejich.
12 tí ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a gbà ní ìní àní pápá oko tútù Ọlọ́run.”
Neboť jsou řekli: Uvažme se dědičně v příbytky Boží.
13 Ìwọ Ọlọ́run, ṣe wọ́n bí ààjà, bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́.
Můj Bože, učiň to, ať jsou jako chumelice, a jako stéblo před větrem.
14 Bí iná ti í jó igbó, àti bí ọ̀wọ́-iná ti ń mú òkè ńlá gbiná,
Jakož oheň spaluje les, a jako plamen zapaluje hory,
15 bẹ́ẹ̀ ni kí o fi ẹ̀fúùfù líle rẹ lépa wọn dẹ́rùbà wọn lójú pẹ̀lú ìjì rẹ.
Tak ty je vichřicí svou stihej, a bouří svou ohrom je.
16 Fi ìtìjú kún ojú wọn, kí àwọn ènìyàn bá à lè ṣe àfẹ́rí orúkọ rẹ àti kí o fi ìjì líle rẹ dẹ́rùbà, ìwọ Olúwa.
Naplň tváře jejich zahanbením, tak aby hledali jména tvého, Hospodine.
17 Jẹ́ kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọ́n sì dààmú láéláé kí wọ́n ṣègbé sínú ẹ̀gàn
Nechať se hanbí a děsí na věčné časy, a ať potupu nesou a zahynou.
18 jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ìwọ, tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa: pé ìwọ nìkan ní Ọ̀gá-ògo jùlọ lórí gbogbo ayé.
A tak ať poznají, že ty, kterýž sám jméno máš Hospodin, jsi nejvyšší nade vší zemí.