< Psalms 82 >

1 Saamu ti Asafu. Ọlọ́run ń ṣàkóso nínú ìpéjọpọ̀ ńlá, ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn “ọlọ́run òrìṣà”.
Psaume d'Asaph. Dieu assiste dans l'assemblée des forts, il juge au milieu des Juges.
2 “Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa gbèjà àwọn aláìṣòdodo kí ó sì ṣe ojú ìṣáájú sí àwọn ènìyàn búburú?
Jusques à quand jugerez-vous injustement, et aurez-vous égard à l'apparence de la personne des méchants? (Sélah)
3 Gbèjà àwọn aláìlágbára àti aláìní baba; ṣe ìtọ́jú ẹ̀tọ́ àwọn aláìní àti ẹni ìnilára.
Faites droit à celui qu'on opprime, et à l'orphelin; faites justice à l'affligé et au pauvre;
4 Gba àwọn aláìlágbára àti aláìní; gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú.
Délivrez celui qu'on maltraite et le misérable, retirez-le de la main des méchants.
5 “Wọn kò mọ̀ ohun kankan, wọn kò lóye ohun kankan. Wọn ń rìn kiri nínú òkùnkùn; à si mí gbogbo ìpìlẹ̀ ayé.
Ils ne connaissent ni n'entendent rien; ils marchent dans les ténèbres, tous les fondements de la terre sont ébranlés.
6 “Mo wí pé, ‘Ẹyin ní “Ọlọ́run òrìṣà”; ẹ̀yin ní gbogbo ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ.’
J'ai dit: vous êtes des dieux, et vous êtes tous enfants du Souverain;
7 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ó kú bí ènìyàn lásán; ẹ̀yin ó ṣubú bí ọ̀kan nínú ọmọ-aládé.”
Toutefois vous mourrez comme les hommes, et vous qui êtes les principaux vous tomberez comme un autre.
8 Dìde, Ọlọ́run, ṣe ìdájọ́ ayé, nítorí gbogbo orílẹ̀-èdè ni ìní rẹ.
Ô Dieu! lève-toi, juge la terre; car tu auras en héritage toutes les nations.

< Psalms 82 >