< Psalms 82 >

1 Saamu ti Asafu. Ọlọ́run ń ṣàkóso nínú ìpéjọpọ̀ ńlá, ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn “ọlọ́run òrìṣà”.
[A Psalm by Asaph.] God presides in the assembly of God. He judges among the gods.
2 “Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa gbèjà àwọn aláìṣòdodo kí ó sì ṣe ojú ìṣáájú sí àwọn ènìyàn búburú?
"How long will you judge unjustly, and show partiality to the wicked?" (Selah)
3 Gbèjà àwọn aláìlágbára àti aláìní baba; ṣe ìtọ́jú ẹ̀tọ́ àwọn aláìní àti ẹni ìnilára.
"Defend the weak, the poor, and the fatherless. Maintain the rights of the poor and oppressed.
4 Gba àwọn aláìlágbára àti aláìní; gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú.
Rescue the weak and needy. Deliver them out of the hand of the wicked."
5 “Wọn kò mọ̀ ohun kankan, wọn kò lóye ohun kankan. Wọn ń rìn kiri nínú òkùnkùn; à si mí gbogbo ìpìlẹ̀ ayé.
They do not know, neither do they understand. They walk back and forth in darkness. All the foundations of the earth are shaken.
6 “Mo wí pé, ‘Ẹyin ní “Ọlọ́run òrìṣà”; ẹ̀yin ní gbogbo ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ.’
I said, "You are gods, all of you are sons of the Most High.
7 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ó kú bí ènìyàn lásán; ẹ̀yin ó ṣubú bí ọ̀kan nínú ọmọ-aládé.”
Nevertheless you shall die like men, and fall like one of the rulers."
8 Dìde, Ọlọ́run, ṣe ìdájọ́ ayé, nítorí gbogbo orílẹ̀-èdè ni ìní rẹ.
Arise, God, judge the earth, for you inherit all of the nations.

< Psalms 82 >