< Psalms 81 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu. Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
Mai marelui muzician, pe o harpă ghitită, un psalm al lui Asaf. Cântați tare lui Dumnezeu, tăria noastră; înălțați sunet de bucurie către Dumnezeul lui Iacob.
2 Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá, tẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
Înălțați un psalm și aduceți tamburina, plăcuta harpă cu psalterionul.
3 Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun àní nígbà tí a yàn; ní ọjọ́ àjọ wa tí ó ní ìrònú.
Sunați trâmbița la luna nouă, la timpul rânduit, în ziua solemnei noastre sărbători.
4 Èyí ni àṣẹ fún Israẹli, àti òfin Ọlọ́run Jakọbu.
Căci acesta a fost un statut pentru Israel și o lege a Dumnezeului lui Iacob.
5 Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu nígbà tí ó la ilẹ̀ Ejibiti já. Níbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
El a rânduit aceasta în Iosif ca mărturie, când a ieșit traversând țara Egiptului, unde eu am auzit o limbă pe care nu am înțeles-o.
6 Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín, a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
Am îndepărtat povara de pe umărul său, mâinile lui au scăpat de coșuri.
7 Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là, mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá, mo dán an yín wò ní odò Meriba. (Sela)
Ai chemat în tulburare și te-am eliberat; ți-am răspuns în locul tainic al tunetului, te-am încercat la apele din Meriba. (Selah)
8 “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín, bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Israẹli.
Ascultă, poporul meu, și îți voi mărturisi; Israele, dacă îmi vei da ascultare,
9 Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín; ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.
Să nu fie niciun dumnezeu străin în tine; nici să nu te închini vreunui dumnezeu străin.
10 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti. Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
Eu sunt DOMNUL Dumnezeul tău, care te-a adus din țara Egiptului, deschide-ți gura larg și o voi umple.
11 “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi; Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
Dar poporul meu a refuzat să dea ascultare vocii mele; și Israel m-a refuzat.
12 Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
Așa că i-am dat poftei inimilor lor și au umblat în propriile lor sfaturi.
13 “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
O, dacă poporul meu mi-ar fi dat ascultare și Israel ar fi umblat în căile mele!
14 ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
Îndată aș fi supus pe dușmanii lor și mi-aș fi întors mâna împotriva potrivnicilor lor.
15 Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀. Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé.
Cei ce îl urăsc pe DOMNUL i s-ar fi supus, iar timpul lor ar fi dăinuit pentru totdeauna.
16 Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”
El i-ar fi hrănit de asemenea cu grăsimea grâului, și te-aș fi săturat cu miere din stâncă.

< Psalms 81 >