< Psalms 81 >
1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu. Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
Para o músico chefe. Sobre um instrumento de Gate. Por Asaph. Sing em voz alta para Deus, nossa força! Faça um grito alegre para o Deus de Jacob!
2 Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá, tẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
Levante uma canção, e traga aqui o pandeiro, a lira agradável com a harpa.
3 Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun àní nígbà tí a yàn; ní ọjọ́ àjọ wa tí ó ní ìrònú.
Blow a trombeta na Lua Nova, na lua cheia, no dia da nossa festa.
4 Èyí ni àṣẹ fún Israẹli, àti òfin Ọlọ́run Jakọbu.
Pois trata-se de um estatuto para Israel, uma ordenança do Deus de Jacob.
5 Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu nígbà tí ó la ilẹ̀ Ejibiti já. Níbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
Ele o nomeou em Joseph para um convênio, quando ele saiu sobre a terra do Egito, Ouvi uma linguagem que eu não conhecia.
6 Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín, a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
“Eu removi seu ombro do fardo. Suas mãos foram liberadas da cesta.
7 Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là, mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá, mo dán an yín wò ní odò Meriba. (Sela)
Você chamou em apuros, e eu o entreguei. Respondi-lhe no lugar secreto dos trovões. Eu te testei nas águas do Meribah”. (Selah)
8 “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín, bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Israẹli.
“Ouça, meu povo, e eu testemunharei a você, Israel, se você me der ouvidos!
9 Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín; ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.
There não deve ser um deus estranho em você, nem adorareis nenhum deus estrangeiro.
10 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti. Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
Eu sou Yahweh, seu Deus, que o trouxeram para fora da terra do Egito. Abra bem a boca, e eu a encherei.
11 “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi; Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
Mas meu povo não deu ouvidos à minha voz. Israel não desejava nenhum de mim.
12 Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
Por isso os deixei ir atrás da teimosia de seus corações, que eles possam caminhar em seus próprios conselhos.
13 “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
Oh que meu povo me escutaria, que Israel caminharia em meus caminhos!
14 ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
Eu logo subjugaria seus inimigos, e virar minha mão contra seus adversários.
15 Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀. Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé.
Os detratores de Yahweh se encolheriam diante dele, e sua punição duraria para sempre.
16 Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”
Mas ele também os teria alimentado com o melhor do trigo. Vou satisfazê-lo com mel fora da rocha”.