< Psalms 81 >
1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu. Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
A karmesternek, a Gittitre. Ászáftól. Ujjongjatok Istennek, a mi erőnknek, riadozzatok Jákób Istenének!
2 Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá, tẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
Hangoztassatok dalt és hallassatok dobot, kedves hárfát, lanttal együtt!
3 Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun àní nígbà tí a yàn; ní ọjọ́ àjọ wa tí ó ní ìrònú.
Fújjátok újholdkor a harsonát, holdtöltekor, ünnepünk napjára.
4 Èyí ni àṣẹ fún Israẹli, àti òfin Ọlọ́run Jakọbu.
Mert törvény az Izraél számára, rendelete Jákób Istenének;
5 Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu nígbà tí ó la ilẹ̀ Ejibiti já. Níbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
bizonyságul tette azt Józsefben, midőn kivonult Egyiptom országa ellen: Nyelvet, melyet nem ismerek, hallok.
6 Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín, a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
Elvontam a tehertől vállát, kezei megszabadultak a kosártól.
7 Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là, mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá, mo dán an yín wò ní odò Meriba. (Sela)
A szorultságban hívtál és kiragadtalak, meghallgattalak a mennydörgés rejtekében, megvizsgáltalak a pörlekedés vizénél. Széla.
8 “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín, bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Israẹli.
Halljad népem, hadd intselek téged, Izraél, bár hallgatnál rám.
9 Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín; ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.
Ne legyen közted idegen isten, s ne borulj le idegen nép istene előtt.
10 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti. Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
Én vagyok az Örökkévaló, a te Istened, aki felhoztalak téged Egyiptom országából: tágra nyisd szájad, megtöltöm azt.
11 “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi; Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
De népem nem hallgatott szavamra, s Izraél nem engedett nekem.
12 Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
Magukra bocsátottam tehát szívük makacságában, járjanak saját tanácsaik szerint.
13 “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
Vajha népem hallgatna reám, Izraél utaim szerint járna:
14 ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
rövidesen megaláznám ellenségeiket, s szorongatóikra fordítanám kezemet;
15 Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀. Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé.
az Örökkévaló gyűlölői hízelegnének neki s örökké tartana az idejük.
16 Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”
Ennie adott búza zsiradékából, és sziklából jóllakattalak mézzel.