< Psalms 81 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu. Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
Au maître-chantre. — D'Asaph. — Sur la Guittith. Chantez avec allégresse en l'honneur de Dieu, notre force; Jetez des cris de joie à la gloire du Dieu de Jacob!
2 Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá, tẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
Entonnez un cantique, faites résonner le tambourin, La douce harpe, avec la lyre.
3 Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun àní nígbà tí a yàn; ní ọjọ́ àjọ wa tí ó ní ìrònú.
Sonnez de la trompette, à la nouvelle lune, A la pleine lune, le jour de notre fête;
4 Èyí ni àṣẹ fún Israẹli, àti òfin Ọlọ́run Jakọbu.
Car c'est une loi pour Israël, Un commandement du Dieu de Jacob.
5 Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu nígbà tí ó la ilẹ̀ Ejibiti já. Níbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
C'est la règle qu'il établit parmi les fils de Joseph, Quand il exerça ses jugements contre le pays d'Egypte. J'entendis alors un langage que je ne connaissais pas:
6 Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín, a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
«J'ai déchargé de son fardeau ton épaule; Tes mains ne sont plus asservies à de durs labeurs.
7 Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là, mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá, mo dán an yín wò ní odò Meriba. (Sela)
Dans ta détresse, tu as crié et je t'ai délivré. Du sein de la tempête dont j'étais enveloppé, J'ai exaucé tes prières; Je t'ai éprouvé aux eaux de Mériba. (Pause)
8 “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín, bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Israẹli.
Écoute, ô mon peuple, et je t'instruirai! O Israël, si tu m'écoutais!
9 Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín; ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.
Qu'il n'y ait au milieu de toi aucun dieu étranger; Ne te prosterne pas devant un autre dieu!
10 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti. Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
Je suis l'Éternel, ton Dieu: Je t'ai fait remonter du pays d'Egypte. Ouvre ta bouche, et je la remplirai.»
11 “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi; Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
Mais mon peuple n'a pas écouté ma voix; Les enfants d'Israël n'ont pas voulu m'obéir.
12 Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
Alors je les ai abandonnés à la dureté de leur coeur, Et ils ont marché au gré de leurs désirs.
13 “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
Oh! si mon peuple voulait m'écouter, Si les enfants d'Israël marchaient dans mes voies!
14 ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
J'aurais bientôt abattu leurs ennemis; Je ferais peser ma main sur leurs adversaires!
15 Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀. Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé.
Ceux qui haïssent l'Éternel viendraient flatter son peuple; Sa prospérité durerait éternellement.
16 Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”
Je vous nourrirais de la moelle du froment; Je vous rassasierais encore du miel du rocher.

< Psalms 81 >