< Psalms 81 >
1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu. Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
For the end, a Psalm for Asaph, concerning the wine presses. Rejoice you in God our helper; shout aloud to the God of Jacob.
2 Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá, tẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
Take a psalm, and produce the timbrel, the pleasant lute with the harp.
3 Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun àní nígbà tí a yàn; ní ọjọ́ àjọ wa tí ó ní ìrònú.
Blow the trumpet at the new moon, in the glorious day of your feast.
4 Èyí ni àṣẹ fún Israẹli, àti òfin Ọlọ́run Jakọbu.
For [this] is an ordinance for Israel, and a statute of the God of Jacob.
5 Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu nígbà tí ó la ilẹ̀ Ejibiti já. Níbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
He made it [to be] a testimony in Joseph, when he came forth out of the land of Egypt: he heard a language which he understood not.
6 Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín, a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
He removed his back from burdens: his hands slaved in making the baskets.
7 Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là, mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá, mo dán an yín wò ní odò Meriba. (Sela)
You did call upon me in trouble, and I delivered you; I heard you in the secret place of the storm: I proved you at the water of Strife. (Pause)
8 “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín, bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Israẹli.
Hear, my people, and I will speak to you, O Israel; and I will testify to you: if you will listen to me;
9 Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín; ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.
there shall be no new god in you; neither shall you worship a strange god.
10 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti. Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
For I am the Lord your God, that brought you out of the land of Egypt: open your mouth wide, and I will fill it.
11 “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi; Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
But my people listened not to my voice; and Israel gave no heed to me.
12 Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
So I let them go after the ways of their own hearts: they will go on in their own ways.
13 “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
If my people had listened to me, if Israel had walked in my ways,
14 ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
I should have put down their enemies very quickly, and should have laid my hand upon those that afflicted them.
15 Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀. Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé.
The Lord's enemies [should have] lied to him: but their time shall be for ever.
16 Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”
And he fed them with the fat of wheat; and satisfied them with honey out of the rock.