< Psalms 8 >
1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Saamu ti Dafidi. Olúwa, Olúwa wa, orúkọ rẹ̀ ti ní ìyìn tó ní gbogbo ayé! Ìwọ ti gbé ògo rẹ ga ju àwọn ọ̀run lọ.
For the Leader; upon the Gittith. A Psalm of David. O LORD, our Lord, how glorious is Thy name in all the earth! whose majesty is rehearsed above the heavens.
2 Láti ẹnu ọmọ ọwọ́ àti ọmọ ọmú ni o ti yan ìyìn nítorí àwọn ọ̀tá rẹ, láti pa àwọn ọ̀tá àti àwọn olùgbẹ̀san lẹ́nu mọ́.
Out of the mouth of babes and sucklings hast Thou founded strength, because of Thine adversaries; that Thou mightest still the enemy and the avenger.
3 Nígbà tí mo ro ọ̀run rẹ, iṣẹ́ ìka rẹ, òṣùpá àti ìràwọ̀, tí ìwọ tí gbé kalẹ̀,
When I behold Thy heavens, the work of Thy fingers, the moon and the stars, which Thou hast established;
4 kí ni ènìyàn tí ìwọ ń rò nípa rẹ̀, àní ọmọ ènìyàn tí ìwọ ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀?
What is man, that Thou art mindful of him? and the son of man, that Thou thinkest of him?
5 Ìwọ ṣe é ní onírẹ̀lẹ̀ díẹ̀ ju Ọlọ́run lọ, ìwọ sì dé e ní adé ògo àti ọlá.
Yet Thou hast made him but little lower than the angels, and hast crowned him with glory and honour.
6 Ìwọ mú un jẹ ọba lórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ rẹ; ìwọ sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀:
Thou hast made him to have dominion over the works of Thy hands; Thou hast put all things under His feet:
7 àwọn agbo àgùntàn àti àwọn màlúù, àti ẹranko igbó,
Sheep and oxen, all of them, yea, and the beasts of the field;
8 ẹyẹ ojú ọrun, àti ẹja inú Òkun, àti ohun tí ń wẹ nínú ipa Òkun.
The fowl of the air, and the fish of the sea; whatsoever passeth through the paths of the seas.
9 Olúwa, Olúwa wa, orúkọ rẹ ti ní ìyìn tó ní gbogbo ayé!
O LORD, our Lord, how glorious is Thy name in all the earth!