< Psalms 79 >

1 Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
Um Salmo por Asaph. Deus, as nações entraram em sua herança. Eles contaminaram seu templo sagrado. Eles colocaram Jerusalém em montões de areia.
2 Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
Eles deram os cadáveres de seus criados para serem alimento para as aves do céu, a carne de seus santos para os animais da terra.
3 Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
Eles derramaram seu sangue como água ao redor de Jerusalém. Não havia ninguém para enterrá-los.
4 Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
We se tornaram uma reprovação para nossos vizinhos, um escárnio e uma zombaria para aqueles que estão ao nosso redor.
5 Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
Quanto tempo, Yahweh? Você vai ficar com raiva para sempre? Seu ciúme vai queimar como fogo?
6 Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
Derrame sua ira sobre as nações que não o conhecem, sobre os reinos que não invocam seu nome,
7 nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
pois eles devoraram Jacob, e destruiu sua pátria.
8 Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
Não nos oponham as iniqüidades de nossos antepassados. Deixe que suas ternas misericórdias nos encontrem rapidamente, pois estamos em necessidade desesperada.
9 Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
Ajude-nos, Deus de nossa salvação, para a glória de seu nome. Entregue-nos, e perdoe nossos pecados, pelo seu nome.
10 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
Por que as nações deveriam dizer: “Onde está seu Deus”? Que seja conhecido entre as nações, diante de nossos olhos, que a vingança pelo sangue de seus servos está sendo derramada.
11 Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
Deixe o suspiro do prisioneiro vir antes de você. De acordo com a grandeza de seu poder, preserve aqueles que são condenados à morte.
12 San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
Retribuir aos vizinhos sete vezes em seu seio a sua reprovação com a qual o censuraram, Senhor.
13 Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.
Portanto, nós, seu povo e as ovelhas de seu pasto, lhe dará graças para sempre. Nós o louvaremos para sempre, a todas as gerações.

< Psalms 79 >