< Psalms 79 >

1 Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
Psaume d'Asaph. Dieu, les nations ont envahi ton héritage; Elles ont profané ton saint temple, Elles ont mis Jérusalem en ruines!
2 Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
Elles ont donné les cadavres de tes serviteurs En pâture aux oiseaux du ciel, La chair de tes fidèles aux bêtes de la terre.
3 Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
Elles ont répandu leur sang comme de l'eau, Autour de Jérusalem, Sans qu'il y eût personne pour les ensevelir.
4 Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
Nous avons été pour nos voisins un objet de mépris, La risée et le jouet de ceux qui nous entourent.
5 Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
Jusques à quand, ô Éternel, t'irriteras-tu sans relâche. Et ta jalousie brûlera-t-elle comme la flamme?
6 Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
Répands ton courroux sur les nations Qui ne te connaissent pas, Sur les royaumes qui n'invoquent pas ton nom!
7 nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
Car ils ont dévoré Jacob, Ils ont désolé sa demeure.
8 Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
Ne nous tiens pas compte de nos iniquités passées. Hâte-toi! Que ta compassion nous vienne en aide! Nous sommes extrêmement misérables!
9 Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
Aide-nous, ô Dieu de notre salut, pour la gloire de ton nom! Délivre-nous! Pardonne nos péchés pour l'amour de ton nom!
10 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
Pourquoi les nations diraient-elles: «Où est leur Dieu?» Fais éclater à nos yeux ta vengeance contre les nations Qui ont répandu le sang de tes serviteurs!
11 Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
Que le gémissement des captifs parvienne jusqu'à toi! Par la force de ton bras, sauve ceux qui sont voués à la mort!
12 San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
Fais retomber sept fois sur la tête de nos voisins, L'outrage qu'ils t'ont infligé, ô Seigneur!
13 Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.
Mais nous, ton peuple, le troupeau dont tu es le berger. Nous te célébrerons à perpétuité. D'âge en âge, nous redirons tes louanges.

< Psalms 79 >