< Psalms 79 >

1 Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
Of Asaph. God, hethene men cam in to thin eritage; thei defouliden thin hooli temple, thei settiden Jerusalem in to the keping of applis.
2 Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
Thei settiden the slayn bodies of thi seruauntis, meetis to the volatilis of heuenes; the fleischis of thi seyntis to the beestis of the erthe.
3 Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
Thei schedden out the blood of hem, as watir in the cumpas of Jerusalem; and noon was that biriede.
4 Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
We ben maad schenschipe to oure neiyboris; mowynge and scornynge to hem, that ben in oure cumpas.
5 Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
Lord, hou longe schalt thou be wrooth in to the ende? schal thi veniaunce be kyndelid as fier?
6 Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
Schede out thin ire in to hethene men, that knowen not thee; and in to rewmes, that clepiden not thi name.
7 nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
For thei eeten Jacob; and maden desolat his place.
8 Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
Haue thou not mynde on oure elde wickidnesses; thi mercies bifore take vs soone, for we ben maad pore greetli.
9 Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
God, oure heelthe, helpe thou vs, and, Lord, for the glorie of thi name delyuer thou vs; and be thou merciful to oure synnes for thi name.
10 Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
Lest perauenture thei seie among hethene men, Where is the God of hem? and be he knowun among naciouns bifore oure iyen. The veniaunce of the blood of thi seruauntis, which is sched out; the weilyng of feterid men entre in thi siyt.
11 Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
Vpe the greetnesse of thin arm; welde thou the sones of slayn men.
12 San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
And yelde thou to oure neiyboris seuenfoold in the bosum of hem; the schenschip of hem, which thei diden schenschipfuli to thee, thou Lord.
13 Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.
But we that ben thi puple, and the scheep of thi leesewe; schulen knouleche to thee in to the world. In generacioun and in to generacioun; we schulen telle thin heriyng.

< Psalms 79 >