< Psalms 78 >

1 Maskili ti Asafu. Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi; tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Asaf'ın Maskili Dinle, ey halkım, öğrettiklerimi, Kulak ver ağzımdan çıkan sözlere.
2 Èmi ó la ẹnu mi ní òwe, èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
Özdeyişlerle söze başlayacağım, Eski sırları anlatacağım,
3 ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
Duyduğumuzu, bildiğimizi, Atalarımızın bize anlattığını.
4 Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ, ní fífi ìyìn Olúwa, àti ipa rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn fún ìran tí ń bọ̀.
Torunlarından bunları gizlemeyeceğiz; RAB'bin övgüye değer işlerini, Gücünü, yaptığı harikaları Gelecek kuşağa duyuracağız.
5 Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli, èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
RAB Yakup soyuna koşullar bildirdi, İsrail'e yasa koydu. Bunları çocuklarına öğretsinler diye Atalarımıza buyruk verdi.
6 nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
Öyle ki, gelecek kuşak, yeni doğacak çocuklar bilsinler, Onlar da kendi çocuklarına anlatsınlar,
7 Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Tanrı'ya güven duysunlar, Tanrı'nın yaptıklarını unutmasınlar, O'nun buyruklarını yerine getirsinler;
8 Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀, ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore, àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
Ataları gibi inatçı, başkaldırıcı, Yüreği kararsız, Tanrı'ya sadakatsiz bir kuşak olmasınlar.
9 Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun, wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
Oklarla, yaylarla kuşanmış Efrayimoğulları Savaş günü sırtlarını döndüler.
10 Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́ wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
Tanrı'nın antlaşmasına uymadılar, O'nun yasasına göre yaşamayı reddettiler.
11 Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe, àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
Unuttular O'nun işlerini, Kendilerine gösterdiği harikaları.
12 Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
Mısır'da, Soan bölgesinde Tanrı harikalar yapmıştı atalarının önünde.
13 Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
Denizi yarıp geçirmişti onları, Bir duvar gibi ayakta tutmuştu suları.
14 Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
Gündüz bulutla, Gece ateş ışığıyla onlara yol göstermişti.
15 Ó sán àpáta ní aginjù ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ẹni pé láti inú ibú wá.
Çölde kayaları yarmış, Sanki dipsiz kaynaklardan Onlara kana kana su içirmişti.
16 Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
Kayadan akarsular fışkırtmış, Suları ırmak gibi akıtmıştı.
17 Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
Ama onlar çölde Yüceler Yücesi'ne başkaldırarak Günah işlemeye devam ettiler.
18 Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
Canlarının çektiği yiyeceği isteyerek İçlerinde Tanrı'yı denediler.
19 Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
“Tanrı çölde sofra kurabilir mi?” diyerek, Tanrı'ya karşı konuştular.
20 Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde, odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
“Bak, kayaya vurunca sular fışkırdı, Dereler taştı. Peki, ekmek de verebilir mi, Et sağlayabilir mi halkına?”
21 Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi; iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu, ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
RAB bunu duyunca çok öfkelendi, Yakup'a ateş püskürdü, Öfkesi tırmandı İsrail'e karşı;
22 nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́, wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
Çünkü Tanrı'ya inanmıyorlardı, O'nun kurtarıcılığına güvenmiyorlardı.
23 Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
Yine de RAB buyruk verdi bulutlara, Kapaklarını açtı göklerin;
24 Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ, ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
Man yağdırdı onları beslemek için, Göksel tahıl verdi onlara.
25 Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli; Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
Meleklerin ekmeğini yedi her biri, Doyasıya yiyecek gönderdi onlara.
26 Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
Doğu rüzgarını estirdi göklerde, Gücüyle güney rüzgarına yol gösterdi.
27 Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀, àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
Toz gibi et yağdırdı başlarına, Deniz kumu kadar kuş;
28 Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn, yíká àgọ́ wọn.
Ordugahlarının ortasına, Konakladıkları yerin çevresine düşürdü.
29 Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
Yediler, tıka basa doydular, İsteklerini yerine getirdi Tanrı.
30 Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún, nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
Ancak onlar isteklerine doymadan, Daha ağızları doluyken,
31 ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn, ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
Tanrı'nın öfkesi parladı üzerlerine. En güçlülerini öldürdü, Yere serdi İsrail yiğitlerini.
32 Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú; nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
Yine de günah işlemeye devam ettiler, O'nun harikalarına inanmadılar.
33 O fi òpin sí ayé wọn nínú asán àti ọdún wọn nínú ìpayà.
Bu yüzden Tanrı onların günlerini boşluk, Yıllarını dehşet içinde bitirdi.
34 Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n, wọn yóò wá a kiri; wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
Tanrı onları öldürdükçe O'na yönelmeye, İstekle O'nu yeniden aramaya başlıyorlardı.
35 Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn; wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
Tanrı'nın kayaları olduğunu, Yüce Tanrı'nın kurtarıcıları olduğunu anımsıyorlardı.
36 Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
Oysa ağızlarıyla O'na yaltaklanıyor, Dilleriyle yalan söylüyorlardı.
37 ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i, wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
O'na yürekten bağlı değillerdi, Antlaşmasına sadık kalmadılar.
38 Síbẹ̀ ó ṣàánú; ó dárí àìṣedéédéé wọn jì òun kò sì pa wọ́n run nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
Yine de Tanrı sevecendi, Suçlarını bağışlıyor, onları yok etmiyordu; Çok kez öfkesini tuttu, Bütün gazabını göstermedi.
39 Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
Onların yalnızca insan olduğunu anımsadı, Geçip giden, dönmeyen bir rüzgar gibi.
40 Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
Çölde kaç kez O'na başkaldırdılar, Issız yerlerde O'nu gücendirdiler!
41 Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò; wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
Defalarca denediler Tanrı'yı, İncittiler İsrail'in Kutsalı'nı.
42 Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀: ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
Anımsamadılar O'nun güçlü elini, Kendilerini düşmandan kurtardığı günü,
43 ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti, àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
Mısır'da gösterdiği belirtileri, Soan bölgesinde yaptığı şaşılası işleri.
44 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀; wọn kò lè mu láti odò wọn.
Mısır'ın kanallarını kana çevirdi, Sularını içemediler.
45 Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run, àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
Gönderdiği at sinekleri yedi halkı, Gönderdiği kurbağalar yok etti ülkeyi.
46 Ó fi ọkà wọn fún láńtata, àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
Ekinlerini tırtıllara, Emeklerinin ürününü çekirgelere verdi.
47 Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
Asmalarını doluyla, Yabanıl incir ağaçlarını iri dolu taneleriyle yok etti.
48 Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín, agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
Büyükbaş hayvanlarını kırgına, Küçükbaş hayvanlarını yıldırıma teslim etti.
49 Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára, ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú, nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
Üzerlerine kızgın öfkesini, Gazap, hışım, bela Ve bir alay kötülük meleği gönderdi.
50 Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀, òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú, ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
Yol verdi öfkesine, Canlarını ölümden esirgemedi, Onları salgın hastalığın pençesine düşürdü.
51 Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti, olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
Mısır'da bütün ilk doğanları, Ham'ın çadırlarında bütün ilk çocukları vurdu.
52 Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran; ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
Kendi halkını davar gibi götürdü, Çölde onları bir sürü gibi güttü.
53 Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
Onlara güvenlik içinde yol gösterdi, korkmadılar; Düşmanlarınıysa deniz yuttu.
54 Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀ òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
Böylece onları kendi kutsal topraklarının sınırına, Sağ elinin kazandığı dağlık bölgeye getirdi.
55 Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní; ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
Önlerinden ulusları kovdu, Mülk olarak topraklarını İsrail oymakları arasında bölüştürdü. Halkını konutlarına yerleştirdi.
56 Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo; wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Ama onlar yüce Tanrı'yı denediler, O'na başkaldırdılar, Koşullarına uymadılar.
57 Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà, wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
Döneklik edip ataları gibi ihanet ettiler, Güvenilmez bir yay gibi bozuk çıktılar.
58 Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn; wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
Puta taptıkları yerlerle O'nu kızdırdılar, Putlarıyla O'nu kıskandırdılar.
59 Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn, inú bí i gidigidi; ó kọ Israẹli pátápátá.
Tanrı bunları duyunca çok öfkelendi, İsrail'i büsbütün reddetti.
60 Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀, àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
İnsanlar arasında kurduğu çadırı, Şilo'daki konutunu terk etti.
61 Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn, dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
Kudretini tutsaklığa, Görkemini düşman eline teslim etti.
62 Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́, ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
Halkını kılıç önüne sürdü, Öfkesini kendi halkından çıkardı.
63 Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn, àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
Gençlerini ateş yuttu, Kızlarına düğün türküsü söylenmez oldu.
64 àfi àlùfáà wọn fún idà, àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
Kâhinleri kılıç altında öldü, Dul kadınları ağlayamadı.
65 Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
O zaman Rab uykudan uyanır gibi, Şarabın rehavetinden ayılan bir yiğit gibi oldu.
66 Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà; ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
Düşmanlarını püskürttü, Onları sonsuz utanca boğdu.
67 Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu, kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
Tanrı Yusuf soyunu reddetti, Efrayim oymağını seçmedi;
68 ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda, òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
Ancak Yahuda oymağını, Sevdiği Siyon Dağı'nı seçti.
69 Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga, gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
Tapınağını doruklar gibi, Sonsuzluk için kurduğu yeryüzü gibi yaptı.
70 Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
Kulu Davut'u seçti, Onu koyun ağılından aldı.
71 Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu àti Israẹli ogún un rẹ̀.
Halkı Yakup'u, kendi halkı İsrail'i gütmek için, Onu yavru kuzuların ardından getirdi.
72 Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn; pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.
Böylece Davut onlara dürüstçe çobanlık etti, Becerikli elleriyle onlara yol gösterdi.

< Psalms 78 >