< Psalms 78 >

1 Maskili ti Asafu. Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi; tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Asafa pamācība. Klausiet, mani ļaudis, manu mācību, atgrieziet savas ausis uz manas mutes valodu.
2 Èmi ó la ẹnu mi ní òwe, èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
Es atdarīšu savu muti sakāmos vārdos un izrunāšu līdzības no veciem laikiem.
3 ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
Ko esam dzirdējuši un zinām, un ko mūsu tēvi mums ir stāstījuši,
4 Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ, ní fífi ìyìn Olúwa, àti ipa rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn fún ìran tí ń bọ̀.
To mēs viņu bērniem neslēpsim, bet izteiksim tiem pēcnākamiem Tā Kunga teicamo slavu un Viņa stiprumu un Viņa brīnumus, ko Viņš darījis.
5 Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli, èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
Jo Viņš ir iecēlis liecību iekš Jēkaba un licis bauslību iekš Israēla, ko Viņš mūsu tēviem pavēlējis, to mācīt saviem bērniem.
6 nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
Ka tie pēcnākamie to zinātu, tie bērni, kas vēl dzims; ka tie celtos un to stāstītu arī saviem bērniem.
7 Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Un ka tie savu cerību liktu uz Dievu un neaizmirstu Dieva darbus, bet sargātu Viņa pavēles;
8 Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀, ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore, àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
Un ka tie nebūtu tādi kā viņu tēvi, atkāpēja un pārgalvīga tauta, kas savā sirdī nebija pastāvīga, un kam gars neturējās pie Dieva.
9 Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun, wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
Efraīma dēli, apbruņoti strēlnieki ar stopiem, atkāpās kaušanas dienā.
10 Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́ wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
Tie neturēja Dieva derību un liedzās staigāt Viņa bauslībā,
11 Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe, àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
Un aizmirsa Viņa darbus un brīnumus, ko Viņš bija parādījis.
12 Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
Viņu tēvu priekšā Viņš darīja brīnumus Ēģiptes zemē, Coana laukā.
13 Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
Viņš pāršķīra jūru un lika tiem cauri iet, un pacēla ūdeņus stāvu kā kopu;
14 Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
Un vadīja tos ar padebesi dienā un cauri nakti ar uguns gaišumu.
15 Ó sán àpáta ní aginjù ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ẹni pé láti inú ibú wá.
Viņš pāršķēla klintis tuksnesī un tos dzirdināja papilnam kā no dziļumiem.
16 Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
Viņš arī izveda upes no akmens un lika tecēt ūdenim straumēm.
17 Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
Taču tie joprojām grēkoja pret Viņu un apkaitināja to Visuaugstāko tuksnesī,
18 Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
Un kārdināja Dievu savā sirdī, barību prasīdami savai dvēselei,
19 Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
Un runāja pret Dievu un sacīja: vai Dievs gan varēs sataisīt galdu tuksnesī?
20 Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde, odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
Redzi, Viņš gan klinti sitis, ka ūdens iztecējis un upes izplūdušas, vai Viņš arī maizi varēs dot, vai Viņš varēs gādāt gaļu Saviem ļaudīm?
21 Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi; iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu, ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
Kad Tas Kungs to dzirdēja, tad tas apskaitās, un uguns iedegās pret Jēkabu, un bardzība cēlās pret Israēli.
22 nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́, wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
Tāpēc, ka tie neticēja uz Dievu, nedz cerēja uz Viņa pestīšanu.
23 Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
Tad Viņš pavēlēja padebešiem augšām un atdarīja debesu durvis,
24 Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ, ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
Un lika mannai uz tiem līt, ko ēst, un deva tiem labību no debesīm.
25 Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli; Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
Ikkurš no tiem ēda debesu maizi, Viņš tiem sūtīja barības papilnam.
26 Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
Viņš lika celties austriņam no debesīm un atveda dienvidus vēju caur savu Spēku,
27 Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀, àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
Un birdināja gaļu uz tiem kā putekļus un spārnainus putnus kā jūras smiltis,
28 Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn, yíká àgọ́ wọn.
Un lika tiem krist viņu lēģera vidū, visapkārt ap viņu dzīvokļiem.
29 Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
Tad tie ēda un pārēdās; un Viņš tiem lika notikt pēc viņu kārības.
30 Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún, nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
Bet pirms tie savu kārību bija pildījuši, kamēr viņu barība vēl bija viņu mutē,
31 ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn, ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
Tad Dieva dusmība pret tiem cēlās un nokāva viņu stipros un nomaitāja Israēla jaunekļus.
32 Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú; nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
Par visu to tie taču vēl vairāk grēkoja un neticēja Viņa brīnumiem.
33 O fi òpin sí ayé wọn nínú asán àti ọdún wọn nínú ìpayà.
Tādēļ Tas nobeidza viņu dzīvību nīcībā un viņu gadus ātrā postā.
34 Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n, wọn yóò wá a kiri; wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
Kad Viņš tos kāva, tad tie vaicāja pēc Viņa un atgriezās un steigšus meklēja Dievu,
35 Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn; wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
Un atminējās, Dievu esam viņiem par patvērumu, un to visaugstāko Dievu esam viņiem par Pestītāju.
36 Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
Un tie Viņam smaidīja ar savu muti un Viņam meloja ar savu mēli.
37 ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i, wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
Jo viņu sirds nepastāvēja pie Viņa, un tie nebija uzticīgi Viņa derībā.
38 Síbẹ̀ ó ṣàánú; ó dárí àìṣedéédéé wọn jì òun kò sì pa wọ́n run nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
Bet Viņš bija sirdsžēlīgs un piedeva noziegumu un tos nesamaitāja, bet novērsa dažkārt Savu dusmību un nepamodināja visu Savu bardzību.
39 Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
Jo Viņš pieminēja, ka tie ir miesa, tā kā vējš, kas aizskrien un atpakaļ negriežas.
40 Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
Cik reiz tie Viņu apkaitināja tuksnesī un Viņu tirināja tai tukšā vietā!
41 Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò; wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
Jo tie kārdināja Dievu allaž no jauna un noskumdināja Israēla svēto.
42 Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀: ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
Tie nepieminēja Viņa roku nedz to dienu, kad Viņš tos no tā spaidītāja izglāba,
43 ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti, àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
Kad Viņš Savas zīmes parādīja Ēģiptē un Savus brīnumus Coana klajumā,
44 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀; wọn kò lè mu láti odò wọn.
Un pārvērta viņu upes par asinīm un viņu strautus, ka nevarēja dzert,
45 Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run, àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
Un sūtīja starp tiem kukaiņus, kas tos ēda, un vardes, kas tos samaitāja,
46 Ó fi ọkà wọn fún láńtata, àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
Un deva viņu augļus spradžiem, un viņu darbus siseņiem,
47 Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
Un nomaitāja viņu vīnakokus caur krusu un viņu vīģes kokus ar lieliem krusas gabaliem,
48 Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín, agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
Un nokāva viņu govis ar krusu un viņu sīkos lopus ar zibeņiem,
49 Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára, ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú, nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
Un uzgāza tiem Savu karsto dusmību, bardzību un postu un bēdas, un uzlaida tiem nelaimes eņģeļus,
50 Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀, òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú, ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
Un deva vaļu Savai dusmībai un neatrāva viņu dvēseles no nāves, un nodeva viņu lopus mērim,
51 Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti, olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
Un kāva visus pirmdzimušos Ēģiptē, vīru pirmdzemdinātos Hama dzīvokļos,
52 Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran; ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
Un veda Savus ļaudis kā avis un vadīja tos tuksnesī kā ganāmu pulku,
53 Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
Un vadīja tos bez bēdām, ka tie nebijās, bet viņu ienaidniekus jūra apklāja.
54 Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀ òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
Un Viņš tos veda Savās svētās robežās, uz šo kalnu, ko Viņa labā roka uzņēmusi.
55 Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní; ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
Un izdzina viņu priekšā pagānus, un tos izdalīja par mantības daļu un Israēla ciltīm lika dzīvot viņu mājās.
56 Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo; wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Taču tie kārdināja un apkaitināja to visuaugstāko Dievu un neturēja Viņa liecības,
57 Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà, wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
Un atkāpās un atmeta ticību, tā kā viņu tēvi; tie atmuka kā viltīgs stops,
58 Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn; wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
Un Viņu apkaitināja ar saviem elku kalniem un to tirināja ar savām bildēm.
59 Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn, inú bí i gidigidi; ó kọ Israẹli pátápátá.
Dievs dzirdēja un apskaitās, un Israēls Tam ļoti rieba.
60 Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀, àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
Un Dievs atstāja to dzīvokli iekš Šīlo, to telti, ko Viņš bija ņēmis par mājas vietu cilvēku starpā.
61 Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn, dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
Un deva viņu spēku cietumā un viņu godību pretinieka rokā;
62 Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́, ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
Un nodeva Savus ļaudis zobenam un apskaitās pret Savu tautu.
63 Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn, àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
Uguns aprija viņu jaunekļus, un viņu jaunavām nedziedāja kāzu dziesmas.
64 àfi àlùfáà wọn fún idà, àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
Viņu priesteri krita caur zobenu, un viņu atraitnes neraudāja.
65 Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
Tad Tas Kungs uzmodās kā viens, kas gulējis, tā kā varonis kliedz, kas vīnu dzēris,
66 Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà; ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
Un sita Savus pretiniekus no aizmugures, un lika tos kaunā uz mūžīgiem laikiem,
67 Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu, kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
Un atmeta Jāzepa dzīvokli, un neizvēlēja Efraīma cilti,
68 ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda, òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
Bet izvēlēja Jūda cilti, Ciānas kalnu, ko Viņš mīlēja;
69 Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga, gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
Un uztaisīja Savu svēto vietu kā debes'augstumu, stipru, kā pasauli, ko uz mūžīgiem laikiem radījis.
70 Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
Un Viņš izredzēja Dāvidu, Savu kalpu, un ņēma to no avju laidariem,
71 Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu àti Israẹli ogún un rẹ̀.
No zīdītāju avīm Viņš tam lika nākt, ganīt Jēkabu, Savu tautu un Israēli, Savu mantību.
72 Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn; pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.
Un viņš tos ganīja ar skaidru sirdi, un tos valdīja ar prātīgu roku.

< Psalms 78 >