< Psalms 78 >

1 Maskili ti Asafu. Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi; tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Hymne d'Asaph. Mon peuple, écoute mes instructions! Prête l'oreille aux paroles de ma bouche!
2 Èmi ó la ẹnu mi ní òwe, èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
J'ouvrirai ma bouche pour prononcer des sentences; Je dirai les mystères des temps anciens.
3 ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
Ce que nous avons entendu et appris à connaître. Ce que nos pères nous ont raconté,
4 Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ, ní fífi ìyìn Olúwa, àti ipa rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn fún ìran tí ń bọ̀.
Nous ne le cacherons point à leurs descendants. Nous raconterons à la génération future les oeuvres glorieuses de l'Éternel, Et sa puissance, et les merveilles qu'il a accomplies.
5 Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli, èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
Il se fit de Jacob le dépositaire de ses révélations; Il établit en Israël une loi. Qu'il ordonna à nos pères d'enseigner à leurs enfants,
6 nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
Pour qu'elle fût connue de la génération suivante, Des enfants qui naîtraient. Et qui viendraient à leur tour la raconter à leurs enfants.
7 Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Ils apprendraient ainsi à mettre en Dieu leur confiance, A ne pas oublier les oeuvres du Dieu fort, A garder ses commandements,
8 Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀, ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore, àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
Et à ne pas devenir, comme leurs pères. Une génération indocile et rebelle. Une génération au coeur inconstant. Et dont l'esprit fut infidèle à Dieu.
9 Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun, wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
Les fils d'Éphraïm, archers habiles à lancer la flèche. Ont tourné le dos le jour du combat.
10 Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́ wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
Ils n'ont point observé l'alliance de Dieu, Et ils ont refusé de suivre sa loi.
11 Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe, àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
Ils ont oublié ses oeuvres. Et les prodiges dont il les avait rendus témoins.
12 Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
En présence de leurs pères, il avait accompli des merveilles Dans le pays d'Egypte, dans les campagnes de Tsoan.
13 Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
Il entr'ouvrit la mer pour leur livrer passage; Il dressa les eaux, pareilles à une digue.
14 Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
Il conduisit son peuple, le jour, par la nuée, Et toute la nuit par l'éclat du feu.
15 Ó sán àpáta ní aginjù ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ẹni pé láti inú ibú wá.
Il fendit des rochers dans le désert, Et il en fit couler des torrents pour le désaltérer.
16 Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
De la pierre, il fit jaillir des ruisseaux; Il en fit sortir des eaux, abondantes comme des fleuves.,
17 Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
Mais ils continuèrent à pécher contre lui, A se révolter dans le désert contre le Très-Haut.
18 Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
Ils tentèrent Dieu dans leur coeur. En demandant une nourriture conforme à leur désir.
19 Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
Ils parlèrent contre Dieu, Et ils dirent: «Dieu pourrait-il Dresser une table dans le désert?
20 Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde, odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
Voici qu'il a frappé le rocher, et les eaux ont coulé, Et des torrents se sont répandus. Mais pourra-t-il donner du pain. Procurer de la viande à son peuple?»
21 Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi; iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu, ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
L'Éternel entendit ces murmures, et il en fut indigné; Son brûlant courroux s'alluma contre Jacob; Sa colère s'éleva contre Israël,
22 nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́, wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
Parce qu'ils n'avaient pas cru en Dieu Et qu'ils ne s'étaient pas confiés en son secours.
23 Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
Alors il donna ses ordres aux nuées d'en haut, Et il ouvrit les portes des cieux.
24 Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ, ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
Il fit pleuvoir sur eux la manne pour les nourrir, Et il leur donna le froment des cieux.
25 Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli; Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
Tous mangèrent le pain des forts; Il leur envoya des vivres à satiété.
26 Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
Il fit souffler le vent d'Orient dans les cieux. Et il fit lever par sa puissance le vent du Midi.
27 Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀, àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
Il fit pleuvoir sur eux de la chair, comme de la poussière. Et des oiseaux, nombreux comme le sable de la mer.
28 Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn, yíká àgọ́ wọn.
Il les fit tomber au milieu de leur camp, Et tout autour de leurs tentes.
29 Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
Ils mangèrent et se rassasièrent abondamment; Il leur accorda tout ce qu'ils avaient désiré.
30 Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún, nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
Ils avaient à peine assouvi leur convoitise, La nourriture était encore dans leur bouche,
31 ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn, ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
Que la colère de Dieu s'éleva contre eux: Il fit périr les hommes les plus robustes. Et il abattit l'élite d'Israël.
32 Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú; nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
Cependant ils péchèrent encore contre Dieu, Et ils ne se laissèrent pas convaincre Par ses oeuvres merveilleuses.
33 O fi òpin sí ayé wọn nínú asán àti ọdún wọn nínú ìpayà.
Alors il fit disparaître leurs jours comme une ombre: Il emporta leurs années dans une ruine soudaine.
34 Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n, wọn yóò wá a kiri; wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
Quand il les faisait mourir, ils le recherchaient; Ils revenaient et s'empressaient de se tourner vers Dieu.
35 Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn; wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
Ils se souvenaient que Dieu était leur rocher, Et le Dieu Très-Haut leur rédempteur.
36 Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
Mais leurs lèvres le trompaient, Et leur langue lui mentait.
37 ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i, wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
Leur coeur ne lui était pas fermement attaché, Et ils n'étaient pas fidèles à son alliance.
38 Síbẹ̀ ó ṣàánú; ó dárí àìṣedéédéé wọn jì òun kò sì pa wọ́n run nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
Mais lui, plein de compassion, pardonnait aux pécheurs Et il ne les détruisait point. Il retint souvent sa colère Et il ne laissa pas se déchaîner son courroux.
39 Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
Il se souvint qu'ils n'étaient que chair, Un souffle qui passe et ne revient plus.
40 Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
Que de fois ils se révoltèrent contre lui dans le désert, Et l'irritèrent dans la solitude!
41 Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò; wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
Ils recommencèrent à tenter Dieu, Et à offenser le Saint d'Israël.
42 Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀: ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
Ils ne se souvinrent plus de ce qu'avait accompli sa main, Le jour où il les délivra de l'oppresseur,
43 ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti, àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
Quand il fit éclater ses prodiges parmi les Égyptiens, Et ses miracles dans les campagnes de Tsoan.
44 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀; wọn kò lè mu láti odò wọn.
Il changea leurs fleuves en sang. Et ils ne purent plus boire à leurs ruisseaux.
45 Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run, àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
Il envoya contre eux des moustiques qui les dévoraient. Et des grenouilles qui infectaient le pays.
46 Ó fi ọkà wọn fún láńtata, àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
Il abandonna leurs récoltes aux sauterelles. Et le fruit de leur travail à leurs essaims.
47 Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
Il fit périr leurs vignes par la grêle, Et leurs sycomores par la gelée.
48 Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín, agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
Il livra leur bétail à la grêle, Et leurs troupeaux à la foudre.
49 Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára, ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú, nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
Il déchaîna contre eux l'ardeur de son courroux, La fureur, l'indignation, la colère. Toute une armée d'anges de malheur.
50 Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀, òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú, ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
Il donna libre cours à sa colère, Et, loin de les préserver de la mort, Il livra leur vie à la destruction.
51 Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti, olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
Il frappa tous les premiers-nés de l'Egypte, Ces prémices de la virilité dans les tentes de Gham,
52 Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran; ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
Puis il emmena son peuple comme un troupeau de brebis; Il le conduisit comme un troupeau à travers le désert.
53 Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
Il dirigea les pas des Israélites, Les préservant de tout danger et de toute crainte. Tandis que la mer engloutissait leurs ennemis.
54 Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀ òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
Il les fit parvenir jusqu'à sa frontière sainte, Jusqu'à la montagne que sa main droite a conquise.
55 Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní; ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
Il chassa des nations devant eux; Il leur en partagea le territoire par le sort, Et il fit habiter les tribus d'Israël sous les tentes de l'ennemi.
56 Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo; wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Mais les Israélites tentèrent le Dieu Très-Haut; Ils se révoltèrent contre lui, Et ils n'observèrent pas ses commandements.
57 Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà, wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
Ils firent défection et furent infidèles comme leurs pères; Ils se détournèrent, pareils à un arc perfide.
58 Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn; wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
Ils l'irritèrent par le culte des hauts-lieux; Et ils excitèrent sa jalousie par leurs idoles.
59 Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn, inú bí i gidigidi; ó kọ Israẹli pátápátá.
A cette vue, Dieu fut indigné; Il prit Israël en profonde aversion.
60 Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀, àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
Il abandonna le tabernacle de Silo, La tente dont il avait fait sa demeure parmi les hommes.
61 Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn, dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
Il laissa emmener en captivité le siège de sa puissance; Il livra sa gloire aux mains de l'ennemi.
62 Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́, ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
Il abandonna son peuple à l'épée, Et s'irrita contre son héritage.
63 Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn, àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
Le feu dévora ses jeunes gens. Et ses vierges furent privées de chants nuptiaux.
64 àfi àlùfáà wọn fún idà, àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
Ses sacrificateurs tombèrent sous les coups de l'épée. Et ses veuves ne purent pas pleurer les morts.
65 Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
Alors le Seigneur se réveilla, Comme un homme qui vient de dormir. Comme un guerrier à qui le vin ferait pousser des cris de joie.
66 Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà; ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
Il refoula ses adversaires; Il leur infligea un opprobre éternel.
67 Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu, kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
Mais il prit en aversion la tente de Joseph, Et il répudia la tribu d'Éphraïm.
68 ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda, òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
Il choisit la tribu de Juda, La montagne de Sion qu'il chérit.
69 Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga, gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
Il y bâtit son sanctuaire, indestructible comme les cieux, Et comme la terre, dont il a posé les fondements pour l'éternité.
70 Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
Il choisit David, son serviteur; Il le prit dans les bergeries.
71 Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu àti Israẹli ogún un rẹ̀.
Il alla le chercher auprès des brebis qui allaitent. Pour faire de lui le berger de Jacob, son peuple. Et d'Israël, son héritage.
72 Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn; pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.
Ainsi David fut pour eux un berger au coeur intègre. Et il les conduisit d'une main prudente.

< Psalms 78 >