< Psalms 78 >

1 Maskili ti Asafu. Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi; tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Une contemplation d'Asaph. Écoutez mon enseignement, mon peuple. Prêtez l'oreille aux paroles de ma bouche.
2 Èmi ó la ẹnu mi ní òwe, èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
J'ouvrirai ma bouche en une parabole. Je vais prononcer les sombres paroles de l'ancien temps,
3 ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
que nous avons entendus et connus, et nos pères nous l'ont dit.
4 Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ, ní fífi ìyìn Olúwa, àti ipa rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn fún ìran tí ń bọ̀.
Nous ne les cacherons pas à leurs enfants, raconter à la génération à venir les louanges de Yahvé, sa force, et les merveilles qu'il a faites.
5 Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli, èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
Car il a établi une alliance en Jacob, et a nommé un enseignant en Israël, qu'il a ordonné à nos pères, qu'ils doivent les faire connaître à leurs enfants;
6 nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
afin que la génération à venir sache, même les enfants qui doivent naître; qui doivent se lever et le dire à leurs enfants,
7 Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
afin qu'ils mettent leur espoir en Dieu, et ne pas oublier les actions de Dieu, mais gardez ses commandements,
8 Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀, ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore, àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
et ne seront pas comme leurs pères... une génération têtue et rebelle, une génération qui n'a pas rendu son cœur loyal, dont l'esprit n'était pas ferme avec Dieu.
9 Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun, wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
Les fils d'Ephraïm, armés et portant des arcs, a fait marche arrière au jour de la bataille.
10 Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́ wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
Ils n'ont pas respecté l'alliance de Dieu, et ont refusé de marcher dans sa loi.
11 Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe, àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
Ils ont oublié ses actions, les merveilles qu'il leur avait montrées.
12 Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
Il a fait des choses merveilleuses aux yeux de leurs pères, dans le pays d'Égypte, dans les champs de Zoan.
13 Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
Il fendit la mer, et les fit passer. Il a fait en sorte que les eaux se dressent comme un tas.
14 Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
Pendant le jour, il les conduisait aussi avec une nuée, et toute la nuit avec une lumière de feu.
15 Ó sán àpáta ní aginjù ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ẹni pé láti inú ibú wá.
Il a fendu des rochers dans le désert, et leur donnait à boire en abondance comme dans les profondeurs.
16 Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
Il a aussi fait jaillir des ruisseaux du rocher, et a fait couler les eaux comme des rivières.
17 Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
Pourtant, ils ont continué à pécher contre lui, pour se rebeller contre le Très-Haut dans le désert.
18 Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
Ils ont tenté Dieu dans leur cœur en demandant de la nourriture selon leur désir.
19 Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
Oui, ils ont parlé contre Dieu. Ils ont dit: « Dieu peut-il préparer une table dans le désert?
20 Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde, odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
Voici, il a frappé le rocher, et les eaux ont jailli, et les ruisseaux ont débordé. Peut-il aussi donner du pain? Fournira-t-il de la viande à son peuple? »
21 Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi; iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu, ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
Yahvé entendit et se mit en colère. Un feu a été allumé contre Jacob, La colère est aussi montée contre Israël,
22 nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́, wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
parce qu'ils ne croyaient pas en Dieu, et n'avait pas confiance en son salut.
23 Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
Pourtant, il a commandé les cieux en haut, et a ouvert les portes du ciel.
24 Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ, ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
Il fit pleuvoir sur eux la manne pour qu'ils la mangent, et leur a donné de la nourriture venant du ciel.
25 Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli; Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
L'homme a mangé le pain des anges. Il leur a envoyé de la nourriture à satiété.
26 Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
Il fit souffler dans le ciel le vent d'est. Par son pouvoir, il a guidé le vent du sud.
27 Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀, àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
Il a aussi fait pleuvoir sur eux de la viande comme de la poussière, des oiseaux ailés comme le sable des mers.
28 Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn, yíká àgọ́ wọn.
Il les fit tomber au milieu de leur camp, autour de leurs habitations.
29 Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
Ils mangèrent donc, et furent rassasiés. Il leur a donné leur propre désir.
30 Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún, nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
Ils ne se sont pas détournés de leurs envies. Leur nourriture était encore dans leur bouche,
31 ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn, ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
quand la colère de Dieu s'est élevée contre eux, a tué certains de leurs plus forts, et a frappé les jeunes hommes d'Israël.
32 Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú; nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
Malgré tout cela, ils ont péché, et ne croyaient pas en ses merveilles.
33 O fi òpin sí ayé wọn nínú asán àti ọdún wọn nínú ìpayà.
C'est pourquoi il a consumé leurs jours dans la vanité, et leurs années de terreur.
34 Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n, wọn yóò wá a kiri; wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
Quand il les a tués, ils ont demandé après lui. Ils sont revenus et ont cherché Dieu avec ardeur.
35 Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn; wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
Ils se sont souvenus que Dieu était leur rocher, le Dieu Très-Haut, leur rédempteur.
36 Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
Mais ils l'ont flatté de leur bouche, et lui ont menti avec leur langue.
37 ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i, wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
Car leur cœur n'était pas droit avec lui, ils n'ont pas été fidèles à son alliance.
38 Síbẹ̀ ó ṣàánú; ó dárí àìṣedéédéé wọn jì òun kò sì pa wọ́n run nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
Mais lui, qui est miséricordieux, pardonna l'iniquité et ne les détruisit pas. Oui, plusieurs fois, il a détourné sa colère, et n'a pas déclenché toute sa colère.
39 Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
Il s'est souvenu qu'ils n'étaient que chair, un vent qui passe et ne revient pas.
40 Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
Combien de fois se sont-ils rebellés contre lui dans le désert, et l'ont affligé dans le désert!
41 Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò; wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
Ils se retournèrent et tentèrent Dieu, et ont provoqué le Saint d'Israël.
42 Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀: ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
Ils ne se sont pas souvenus de sa main, ni le jour où il les a rachetés à l'adversaire;
43 ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti, àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
comment il a placé ses signes en Égypte, ses merveilles dans le champ de Zoan,
44 Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀; wọn kò lè mu láti odò wọn.
il a changé leurs fleuves en sang, et leurs ruisseaux, de sorte qu'ils ne pouvaient pas boire.
45 Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run, àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
Il envoya parmi eux des nuées de mouches, qui les dévorèrent; et des grenouilles, qui les ont détruits.
46 Ó fi ọkà wọn fún láńtata, àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
Il a aussi donné leur accroissement à la chenille, et leur travail à la sauterelle.
47 Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
Il a détruit leurs vignes par la grêle, leurs figuiers sycomores avec le gel.
48 Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín, agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
Il a aussi livré leur bétail à la grêle, et leurs troupeaux à de chauds coups de foudre.
49 Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára, ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú, nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
Il a jeté sur eux l'ardeur de sa colère, la colère, l'indignation et le trouble, et une bande d'anges du mal.
50 Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀, òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú, ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
Il a tracé un chemin pour sa colère. Il n'a pas épargné leur âme de la mort, mais ont donné leur vie à la peste,
51 Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti, olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
et frappa tous les premiers-nés d'Égypte, le chef de leur force dans les tentes de Ham.
52 Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran; ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
Mais il a conduit son propre peuple comme des moutons, et les a guidés dans le désert comme un troupeau.
53 Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
Il les a conduits en toute sécurité, de sorte qu'ils n'ont pas eu peur, mais la mer a submergé leurs ennemis.
54 Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀ òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
Il les amena jusqu'à la frontière de son sanctuaire, à cette montagne, que sa main droite avait prise.
55 Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní; ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
Il a aussi chassé les nations devant eux, les a attribués en héritage par ligne, et a fait habiter les tribus d'Israël dans leurs tentes.
56 Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo; wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
Pourtant, ils ont tenté et se sont rebellés contre le Dieu Très-Haut, et n'a pas gardé ses témoignages,
57 Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà, wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
mais ils se sont détournés, et ont agi avec perfidie comme leurs pères. Ils étaient tordus comme un arc trompeur.
58 Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn; wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
Car ils l'ont irrité par leurs hauts lieux, et l'ont rendu jaloux avec leurs images gravées.
59 Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn, inú bí i gidigidi; ó kọ Israẹli pátápátá.
Lorsque Dieu a entendu cela, il s'est mis en colère, et abhorrait fortement Israël,
60 Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀, àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
de sorte qu'il abandonna la tente de Silo, la tente qu'il a placée parmi les hommes,
61 Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn, dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
et a livré sa force en captivité, sa gloire dans la main de l'adversaire.
62 Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́, ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
Il a aussi livré son peuple à l'épée, et était en colère contre son héritage.
63 Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn, àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
Le feu a dévoré leurs jeunes hommes. Leurs vierges n'ont pas eu de chanson de mariage.
64 àfi àlùfáà wọn fún idà, àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
Leurs prêtres sont tombés par l'épée, et leurs veuves ne pouvaient pas pleurer.
65 Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
Alors le Seigneur se réveilla comme quelqu'un qui sort du sommeil, comme un homme puissant qui crie à cause du vin.
66 Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà; ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
Il a frappé ses adversaires en arrière. Il les a soumis à un reproche perpétuel.
67 Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu, kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
De plus, il rejeta la tente de Joseph, et n'a pas choisi la tribu d'Ephraïm,
68 ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda, òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
Mais il choisit la tribu de Juda, Le mont Sion qu'il aimait.
69 Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga, gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
Il a construit son sanctuaire comme les hauteurs, comme la terre qu'il a établie pour toujours.
70 Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
Il a aussi choisi David, son serviteur, et l'ont pris dans les bergeries;
71 Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu àti Israẹli ogún un rẹ̀.
de suivre les brebis qui ont leurs petits, il l'a amené à être le berger de Jacob, son peuple, et Israël, son héritage.
72 Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn; pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.
Il a doncété leur berger selon l'intégrité de son cœur, et les a guidés par l'habileté de ses mains.

< Psalms 78 >