< Psalms 77 >

1 Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
Asaf dwom. Misu mefrɛɛ Onyankopɔn srɛɛ mmoa; misu mefrɛɛ no sɛ ontie me.
2 Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
Bere a mewɔ ahohiahia mu no, mehwehwɛɛ Awurade; metrɛw me nsa a ɛmpa abaw mu anadwo na me kra ampene sɛ wɔbɛkyekye ne werɛ.
3 Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
Onyankopɔn mekaee wo, na misii apini; medwenee, na me honhom tɔɔ beraw.
4 Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
Woamma mʼani ankum; amanehunu dodow nti, mantumi ankasa.
5 Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
Medwenee nna a atwam no ho, teteete mfe no ho;
6 mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
mekaee me nnwom a na meto no anadwo. Me koma dwenee ho na me honhom bisae se:
7 “Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
“Enti, Awurade bɛpo yɛn daa? Ɔrenhu yɛn mmɔbɔ bio ana?
8 Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
Nʼadɔe a ɛnsa da atu ayera koraa ana? Na ne bɔhyɛ no, amma mu koraa ana?
9 Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
Onyankopɔn werɛ afi sɛ ɔbɛyɛ mmɔborɔhunufo ana? Ɔde abufuw atwe nʼayamhyehye no asan ana?”
10 Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
Afei misusuwii se, “Eyi de, mɛsrɛ: mfe a Ɔsorosoroni no teɛɛ ne nsa nifa mu no.”
11 Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
Mɛkae nneɛma a Awurade ayɛ; yiw, mɛkae wo tete anwonwade no.
12 Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
Mɛdwene wo nnwuma nyinaa ho na masusuw wo nneyɛe akɛse nyinaa ho.
13 Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
Onyankopɔn, wʼakwan yɛ kronkron. Onyame bɛn na ɔso sɛ yɛn Nyankopɔn?
14 Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
Wone Onyankopɔn a woyɛ anwonwade; wokyerɛ wo tumi wɔ aman mu.
15 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
Wode wo tumi nsa no gyee wo nkurɔfo, Yakob ne Yosef asefo no.
16 Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
Onyankopɔn, nsu no huu wo, nsu no huu wo na wɔpopoe; bun no mpo ho wosowee.
17 Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
Omununkum tɔɔ nsu, aprannaa gyigyee wɔ ɔsoro; na wo bɛmma paa gya dii akɔneaba.
18 Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
Wʼaprannaa bobɔɔ mu wɔ mfɛtɛ no mu, wʼanyinam hyerɛn wiase; asase popoe, na ɛwosowee.
19 Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
Wode wo kwan faa po mu, wode faa nsu kɛse mu, nanso wɔanhu wʼanammɔn.
20 Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Wonam Mose ne Aaron abasa so, dii wo nkurɔfo anim sɛ nguankuw.

< Psalms 77 >