< Psalms 77 >

1 Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
Au maître-chantre. — Selon Jéduthun. — Psaume d'Asaph. Ma voix s'adresse à Dieu, et je crie; Ma voix s'adresse à Dieu, afin qu'il m'écoute.
2 Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
Au jour de ma détresse, je cherche le Seigneur; La nuit, ma main est tendue vers lui et ne se lasse point; Mon âme refuse d'être consolée.
3 Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
Je me souviens de Dieu, et je gémis; Je médite, et mon esprit est abattu. (Pause)
4 Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
Tu tiens mes paupières ouvertes; Je suis troublé, je ne puis parler.
5 Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
Je pense aux jours d'autrefois. Aux années des temps passés.
6 mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
Je me souviens de mes cantiques pendant la nuit; Je médite en mon coeur. Mon esprit se demande:
7 “Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
«Le Seigneur nous rejettera-t-il éternellement? Ne sera-t-il plus jamais propice?
8 Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
Sa bonté est-elle à jamais épuisée? Sa promesse est-elle anéantie pour toujours?
9 Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
Dieu a-t-il oublié d'avoir pitié? A-t-il, dans sa colère, mis un terme à ses compassions?» (Pause)
10 Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
Puis je me dis: «Voici la cause de ma souffrance: C'est que la main droite du Très-Haut a changé»
11 Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
Je me rappellerai donc les actions glorieuses de l'Éternel. Oui, je me souviendrai de tes merveilles d'autrefois;
12 Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
Je penserai à toutes tes oeuvres, Et j'évoquerai le souvenir de tes prodiges!
13 Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
Ô Dieu, tes voies sont saintes! Quel Dieu est grand comme notre Dieu?
14 Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
Tu es le Dieu qui accomplit des merveilles; Tu as fait connaître parmi les peuples ta puissance.
15 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
Par ton bras, tu as délivré ton peuple, Les enfants de Jacob et de Joseph. (Pause)
16 Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
Les eaux t'ont vu, ô Dieu! Les eaux t'ont vu, elles ont frémi; Même les abîmes furent ébranlés.
17 Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
Les nuées se répandirent en torrents d'eau; Les nuages lancèrent la foudre Et tes flèches volèrent de toutes parts.
18 Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
Ton tonnerre gronda dans le tourbillon; Les éclairs illuminèrent le monde; La terre fut ébranlée et trembla.
19 Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
Tu te fis un chemin dans la mer, Un sentier dans les grandes eaux, Sans qu'on pût reconnaître tes traces.
20 Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Tu as conduit ton peuple comme un troupeau, Par la main de Moïse et d'Aaron.

< Psalms 77 >