< Psalms 77 >

1 Fún adarí orin. Fún Jedutuni. Ti Asafu. Saamu. Mó kígbe sí Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́; mo kígbe sí Ọlọ́run láti gbọ́ tèmi.
Přednímu kantoru z potomků Jedutunových, s Azafem, žalm. Hlas můj k Bohu, když volám, hlas můj k Bohu, aby ucha naklonil ke mně.
2 Nígbà tí mo wà nínú ìpọ́njú, mo wá Olúwa; ní òru ni mo na ọwọ́ mi jáde ní àìkáárẹ̀ ọkàn mí sì kọ̀ láti tù ú nínú.
V den ssoužení svého Pána hledal jsem, v noci ruce své rozprostíral jsem bez přestání, a nedala se potěšiti duše má.
3 Èmi rántí rẹ, Ọlọ́run, mo sì kẹ́dùn; mo ṣe àròyé, ẹ̀mí mi sì rẹ̀wẹ̀sì. (Sela)
Na Boha zpomínal jsem a kormoutil se, přemyšloval jsem, a úzkostmi svírán byl duch můj. (Sélah)
4 Ìwọ kò fẹ́ kí èmi fi ojú ba oorun, mo dààmú tó bẹ́ẹ̀ tí ń kò le sọ̀rọ̀.
Zdržoval jsi oči mé, aby bděly; potřín jsem byl, aniž jsem mluviti mohl.
5 Mo ronú nípa ọjọ́ ìgbàanì; ọdún pípẹ́ sẹ́yìn;
I přicházeli mi na pamět dnové předešlí, a léta dávní.
6 mo rántí orin mi ní òru. Èmi ń bá àyà mi sọ̀rọ̀, ọkàn mi sì ń ṣe àwárí jọjọ.
Rozpomínal jsem se v noci na zpěvy své, v srdci svém přemyšloval jsem, a zpytoval to duch můj, pravě:
7 “Olúwa yóò ha kọ̀ títí láé? Ki yóò ha ṣe ojúrere rẹ̀ mọ́?
Zdali na věky zažene Bůh? Nikdy-liž již více lásky neukáže?
8 Ṣe ìfẹ́ rẹ̀ àti àánú rẹ̀ ti kú lọ láéláé? Ìlérí rẹ̀ ha kùnà títí ayé?
Zdali do konce přestane milosrdenství jeho? A konec vezme slovo od pokolení až do pokolení?
9 Ọlọ́run ha gbàgbé láti máa ṣàánú? Ní ìbínú rẹ̀, ó ha sé ojúrere rẹ̀ mọ́?” (Sela)
Zdali se zapomněl smilovávati Bůh silný? Zdaž zadržel v hněvě milosrdenství svá? (Sélah)
10 Èmi wí pé, “Èyí ní ẹ̀dùn ọkàn mi, pé ọwọ́ ọ̀tún Ọ̀gá-ògo jùlọ ti yípadà”.
I řekl jsem: Toť jest má smrt. Ale učiníť proměnu pravice Nejvyššího.
11 Èmi ó rántí iṣẹ́ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni, èmi ó rántí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ ọjọ́ pípẹ́.
Rozpomínati se budu na skutky Hospodinovy, a připomínati sobě divné činy tvé, od starodávna.
12 Èmi ṣàṣàrò lórí iṣẹ́ rẹ gbogbo, pẹ̀lú, ènìyàn sì máa sọ̀rọ̀ gbogbo iṣẹ́ agbára rẹ.
A přemyšlovati o všelikém díle tvém, a o skutcích tvých mluviti.
13 Ọlọ́run, ọ̀nà rẹ jẹ́ mímọ́. Ọlọ́run wo ni ó sì tóbi bí Ọlọ́run wa?
Bože, svatá jest cesta tvá. Kdo jest silný, veliký, jako Bůh?
14 Ìwọ ni Ọlọ́run tó ń ṣe ìyanu; ìwọ fi agbára rẹ hàn nínú àwọn ènìyàn.
Ty jsi ten Bůh silný, jenž činíš divné věci; uvedl jsi v známost mezi národy sílu svou.
15 Pẹ̀lú ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ ra àwọn ènìyàn padà, àwọn ọmọ Jakọbu àti Josẹfu. (Sela)
Vysvobodil jsi ramenem lid svůj, syny Jákobovy a Jozefovy. (Sélah)
16 Nígbà tí àwọn omi rí Ọlọ́run, nígbà tí àwọn omi rí ọ, ẹ̀rù bà wọ́n, nítòótọ́ ara ibú kò balẹ̀.
Vidělyť jsou tě vody, Bože, viděly tě vody, a zstrašily se; pohnuly se také i hlubiny.
17 Àwọn ojú ọ̀run tú omi sílẹ̀, àwọsánmọ̀ fi àrá dáhùn; ọfà rẹ̀ ń tàn sẹ́yìn àti síwájú.
Vydali povodně oblakové, vydala hřmot nebesa, ano i kameníčko tvé skákalo.
18 Àrá rẹ̀ ni a gbọ́ nínú ìjì, ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ mọ́lẹ̀ sí gbogbo ayé; ayé bẹ̀rù, wọ́n sì wárìrì.
Vznělo hřímání tvé po obloze, blýskání osvěcovalo okršlek zemský, pohybovala se a třásla země.
19 Ipa rẹ̀ gba Òkun, ọ̀nà rẹ̀ ń bẹ nínú Òkun, ọ̀nà la omi alágbára kọjá ipa rẹ̀ ń bẹ nínú líla omi alágbára kọjá, nítòótọ́ a kò rí ojú ẹsẹ̀ rẹ̀.
Skrze moře byla cesta tvá, a stezky tvé skrze vody veliké, a však šlepějí tvých nebylo znáti.
20 Ó tọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Vedl jsi jako stádo lid svůj skrze Mojžíše a Arona.

< Psalms 77 >