< Psalms 76 >
1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Asafu. Orin. Ní Juda ni a mọ Ọlọ́run; orúkọ rẹ̀ sì lágbára ní Israẹli
Načelniku godbe na strune, psalm Asafu in pesem. Plemenit je v Judi Bog, v Izraelu veliko ime njegovo.
2 Àgọ́ rẹ̀ wà ní Salẹmu, ibùgbé rẹ̀ ni Sioni.
V Salemu je koča njegova, in prebivališče na Sijonu.
3 Níbẹ̀ ni ó ṣẹ́ ọfà, asà àti àwọn idà, ohun ìjà ogun. (Sela)
Ondi je zlomil loke bliskajoče, ščit in meč in vojsko presilno.
4 Ìwọ ni ògo àti ọlá, ju òkè ńlá ìkógun wọ̀nyí lọ.
Svetál si postal, veličasten, z gorâ plenjenja.
5 A kó àwọn alágídí ọkàn ní ìkógun wọ́n sun oorun ìgbẹ̀yìn wọn; kò sí ọ̀kan nínú àwọn akọni tó lè gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè.
V plen so se dali krepki v srci; spali so spanje svoje; tako da niso našli nobeni možje vojaki svojih rók.
6 Ní ìfibú rẹ, Ọlọ́run Jakọbu, àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.
Od hudovanja tvojega, o Bog Jakobov, onemogel je voz in konj.
7 Ìwọ nìkan ni ó yẹ kí a bẹ̀rù. Ta ló lé dúró níwájú rẹ, nígbà tí ìwọ bá ń bínú?
Ti, tí si strašán, ali bi kdo obstal pred teboj, odkar se jeziš?
8 Ìwọ ń ṣe ìdájọ́ láti ọ̀run, ilé ayé bẹ̀rù, ó sì dúró jẹ́ẹ́,
Z neba daješ, da se čuje sodba, zemlja se boji in se je umirila,
9 nígbà tí, ìwọ Ọlọ́run, bá dìde láti ṣe ìdájọ́, láti gba àwọn ẹni ìnilára ilẹ̀ náà. (Sela)
Ko vstane na sodbo Bog, branit vse krotke na zemlji.
10 Lóòótọ́, ìbínú rẹ sí àwọn ènìyàn ń mú ìyìn wá fún ọ, ẹni tí ó yọ nínú ìbínú rẹ ní a dá nígbà tí ìwọ bá fi ìbínú ìyókù di ara rẹ ni àmùrè.
Ker srd človeški te slaví, z ostanki srda opasuješ svoje.
11 Jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì mú un ṣẹ; kí gbogbo àwọn tí ó yí i ká mú ẹ̀bùn wá fún ẹni tí ó tọ́ láti bẹ̀rù.
Delajte in opravljajte obljube Gospodu Bogu svojemu; katerikoli stojé okolo njega, prinesó naj mu dar strašnemu,
12 Ó ké ẹ̀mí àwọn aládé kúrò; àwọn ọba ayé sì ń bẹ̀rù rẹ̀.
Kateri žanje napuh prvakov, strašán zemeljskim kraljem.