< Psalms 75 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn, “Má ṣe parun.” Saamu ti Asafu. Orin. A fi ìyìn fún ọ, Ọlọ́run, a yìn ọ́, nítorí orúkọ rẹ súnmọ́ tòsí; àwọn ènìyàn ń sọ ti ìyanu rẹ.
Au maître-chantre. — «Ne détruis pas». — Psaume d'Asaph. — Cantique. Nous te louons, ô Dieu, nous célébrons tes louanges. Et ton nom est présent parmi nous. Tous racontent tes merveilles.
2 Ìwọ wí pé, “Mo yan àkókò ìyàsọ́tọ̀; Èmi ni ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ òdodo.
«Quand viendra le jour fixé par moi, dit le Seigneur, Je jugerai avec équité.
3 Nígbà tí ayé àti àwọn ènìyàn ibẹ̀ wárìrì, Èmi ni mo di òpó rẹ̀ mú ṣinṣin.
La terre chancelait avec tous ses habitants; Moi, j'en affermis les colonnes.» (Pause)
4 Èmí wí fún àwọn agbéraga pé, ẹ má ṣe gbéraga mọ́; àti sí ènìyàn búburú; ẹ má ṣe gbé ìwo yín sókè.
Je dis aux orgueilleux: «Ne vous enorgueillissez pas. Et aux méchants: «Ne levez pas la tête;
5 Ẹ má ṣe gbe ìwo yín sókè sí ọ̀run; ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọrùn líle.”
Ne levez pas si haut votre tête; Ne parlez pas avec insolence en raidissant le cou!»
6 Nítorí ìgbéga kò ti ìlà-oòrùn wá tàbí ní ìwọ̀-oòrùn, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe láti gúúsù wá.
Car ce n'est pas de l'Orient, ni de l'Occident, Ni du désert, que vient la prospérité;
7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni olùdájọ́; Ó ń rẹ ẹnìkan sílẹ̀, ó sì ń gbé ẹlòmíràn ga.
Mais c'est Dieu qui juge: Il abaisse l'un, et il élève l'autre.
8 Ní ọwọ́ Olúwa ni ago kan wà, ọtí wáìnì náà sì pọ́n, ó kún fún àdàlú, ó fún ọtí àdàlú tí a pò mọ́ òórùn dídùn tí ó tú jáde, àwọn ènìyàn búburú ayé gbogbo mú u pátápátá.
L'Éternel tient dans sa main une coupe, Où écume un vin mélangé d'aromates; Il verse à boire à tous les méchants de la terre: Ils videront la coupe jusqu'à la lie!
9 Ṣùgbọ́n èmi, ó máa ròyìn rẹ títí láé; èmi ó kọrin ìyìn sí Ọlọ́run Jakọbu.
Voilà ce que je ne cesserai pas de redire. En chantant à la gloire du Dieu de Jacob.
10 Èmi ó gé ìwo gbogbo ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ìwo àwọn olódodo ni a ó gbéga.
Je briserai entièrement la puissance des méchants; Mais le juste verra grandir sa puissance.

< Psalms 75 >