< Psalms 73 >
1 Saamu ti Asafu. Nítòótọ́ Ọlọ́run dára fún Israẹli, fún àwọn ọlọ́kàn funfun.
Aszáf zsoltára. Bizony jó Izráelhez az Isten, azokhoz, a kik tiszta szívűek.
2 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi, ẹsẹ̀ mi ti yẹ̀ tán; ìrìn mi fẹ́rẹ̀ yọ̀ tán.
De én?! Már-már meghanyatlottak lábaim; és kis híjja, hogy lépteim el nem iszamodtak.
3 Nítorí èmi ń ṣe ìlara àwọn tó ń ṣe féfé nígbà tí mo bá rí àlàáfíà àwọn ènìyàn búburú.
Mert irígykedtem a kevélyekre, látván a gonoszok jó szerencséjét.
4 Wọn kò ṣe wàhálà; ara wọn mókun wọn sì lágbára.
Mert halálukig nincsenek kínjaik, és az ő erejök állandó.
5 Wọn kò ní ìpín nínú àjàgà tó ń ṣẹlẹ̀ sí ènìyàn; a kò pọ́n wọn lójú nípa ẹlòmíràn.
A halandók nyomorúságában nincs részök, és az emberekkel nem ostoroztatnak.
6 Ìgbéraga ni ọ̀ṣọ́ ọrùn wọn; ìwà ipá bò wọ́n mọ́lẹ̀ bí aṣọ.
Ezért nyakuknak ékessége kevélység, ruha gyanánt erőszak borítja őket.
7 Láti inú ọkàn àrékérekè ni àìṣòdodo ti wá; ẹ̀rí ọkàn búburú wọn kò ní òdínwọ̀n.
A kövérség miatt kinn ülnek az ő szemeik, elméjök gondolatjai csaponganak.
8 Wọn ń ṣẹ̀sín, wọn sì ń sọ̀rọ̀-òdì ní ti ìnilára, wọ́n ń sọ̀rọ̀ láti ibi gíga.
Gúnyolódnak és gonoszságot szólnak; elnyomásról beszélnek fennhéjázással.
9 Wọ́n ń gbé ẹ̀mí wọn lé ọ̀run ahọ́n wọn gba ipò ayé.
Az égre tátogatják szájokat, és nyelvök eljárja a földet.
10 Nítorí náà àwọn ènìyàn wọn yípadà sí wọn wọ́n sì mu omi ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Azért fordul az ő népe ide, hogy tele pohár vizet szürcsölnek;
11 Wọ́n wí pé, “Báwo ni Ọlọ́run yóò ṣe mọ̀? Ọ̀gá-ògo ha ní ìmọ̀ bí?”
És mondják: Mint tudhatná ezt az Isten, s van-é a Magasságosban értelem?
12 Bí àwọn ènìyàn búburú ṣe rí nìyí, ènìyàn asán, wọ́n ń pọ̀ ní ọrọ̀.
Ímé, ezek gonoszok, és örök biztonságban vagyont gyűjtenek!
13 Nítòótọ́ nínú asán ni mo pa ọkàn mi mọ́; nínú asán ni mo wẹ ọwọ́ mi ní àìlẹ́ṣẹ̀.
Bizony hiába tartottam én tisztán szívemet, és mostam ártatlanságban kezeimet;
14 Ní gbogbo ọjọ́ ni a ń yọ mí lẹ́nu; a sì ń jẹ mí ní yà ní gbogbo òwúrọ̀.
Mert nyomorgattatom minden napon, és ostoroztatom minden reggel!
15 Bí mo bá wí pé, “Èmi ó wí báyìí,” èmi ó ṣẹ̀ sí ìran àwọn ọmọ rẹ̀.
Ha azt mondom: Ilyen módon szólok: Ímé, a te fiaid nemzedékét árulom el.
16 Nígbà tí mo gbìyànjú láti mọ èyí, Ó jẹ́ ìnilára fún mi,
Gondolkodom, hogy ezt megérthessem; de nehéz dolog ez szemeimben.
17 títí mo fi wọ ibi mímọ́ Ọlọ́run; nígbà náà ni òye ìgbẹ̀yìn wọn yé mi.
Mígnem bemenék az Isten szent helyébe: megértém azoknak sorsát.
18 Lóòtítọ́ ìwọ gbé wọn lórí ilẹ̀ yíyọ́ ìwọ jù wọ́n sílẹ̀ sínú ìparun.
Bizony síkos földön helyezted el őket; pusztaságokra vetetted ki őket.
19 Báwo ní a ti mú wọn lọ sínú ìdahoro yìí bí ẹni pé ní ìṣẹ́jú kan! Ìbẹ̀rù ni a fi ń run wọ́n pátápátá!
Mind elpusztulnak egy szempillantásban! Elvesznek, elenyésznek a rettegéstől.
20 Bí àlá nígbà tí ènìyàn bá jí, bẹ́ẹ̀ ni nígbà tí ìwọ bá dìde, Olúwa, ìwọ yóò ṣe àbùkù àwòrán wọn.
Mint álmot, ha felserkenünk: te Uram, ha felserkensz, úgy veted meg képöket.
21 Nígbà tí inú mi bàjẹ́ àti ọkàn mi ṣì korò,
Hogyha keseregne szívem, és háborognának veséim:
22 mo jẹ́ aṣiwèrè àti aláìlóye; mo jẹ́ ẹranko ní iwájú rẹ.
Akkor balgatag és tudatlan volnék én, oktalan állat volnék te irántad.
23 Síbẹ̀ mo wà pẹ̀lú rẹ nígbà gbogbo; ìwọ di ọwọ́ ọ̀tún mi mú.
De én mindenkor veled vagyok, te fogod az én jobb kezemet.
24 Ìwọ fi ìmọ̀ràn rẹ tọ́ mi ní ìkẹyìn ìwọ ó mú mi lọ sí inú ògo.
Tanácsoddal igazgatsz engem, és azután dicsőségbe fogadsz be engem.
25 Ta ni mo ní ní ọ̀run, bí kò ṣe ìwọ? Àti ní ayé kò sí ohun tí mo fẹ́ lẹ́yìn rẹ.
Kicsodám van az egekben? Náladnál egyébben nem gyönyörködöm e földön!
26 Ara mi àti ọkàn mi le è kùnà ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni agbára ẹ̀mí mi àti ìpín mi títí láé.
Ha elfogyatkozik is testem és szívem: szívemnek kősziklája és az én örökségem te vagy, oh Isten, mindörökké!
27 Àwọn tí ó jìnnà sí ọ yóò ṣègbé ìwọ ti pa gbogbo wọn run; tí ń ṣe àgbèrè kiri kúrò lọ́dọ̀ rẹ.
Mert ímé, a kik eltávoznak tőled, elvesznek; mind kiirtod azokat, a kik elhajolnak tőled.
28 Ṣùgbọ́n ní ti èmi, ó dára láti súnmọ́ Ọlọ́run. Èmi ti fi Olúwa Olódùmarè ṣe ààbò mi; kí èmi ó lè máa sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ.
De én? Isten közelsége oly igen jó nékem. Az Úr Istenben vetem reménységemet, hogy hirdessem minden te cselekedetedet.